-
“Ọgbọ́n Jẹ́ Fún Ìdáàbòbò”Ilé Ìṣọ́—2007 | July 15
-
-
Báwo ló ṣe yẹ kí ọgbọ́n tá a ní máa hàn nínú ọ̀rọ̀ tá à ń sọ? Ọlọ́gbọ́n ọba náà dáhùn, ó ní: “Ẹni tí ń fi ìjìnlẹ̀ òye hàn nínú ọ̀ràn yóò rí ire, aláyọ̀ sì ni ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. Ẹni tí ó gbọ́n ní ọkàn-àyà ni a ó pè ní olóye, ẹni tí ètè rẹ̀ sì dùn ń fi ìyíniléròpadà kún un. Ìjìnlẹ̀ òye jẹ́ kànga ìyè fún àwọn tí ó ni ín; ìbáwí àwọn òmùgọ̀ sì ni ìwà òmùgọ̀. Ọkàn-àyà ọlọ́gbọ́n ń mú kí ẹnu rẹ̀ fi ìjìnlẹ̀ òye hàn, èyí sì ń fi ìyíniléròpadà kún ètè rẹ̀.”—Òwe 16:20-23.
-
-
“Ọgbọ́n Jẹ́ Fún Ìdáàbòbò”Ilé Ìṣọ́—2007 | July 15
-
-
Abájọ tí wọ́n ṣe máa ń pe “ẹni tí ó gbọ́n ní ọkàn-àyà” ní “amòye”! (Òwe 16:21, Bibeli Mimọ) Láìṣe àní-àní, “kànga ìyè” ni ìjìnlẹ̀ òye jẹ́ fáwọn tó ní in. Kí ló máa wá ṣẹlẹ̀ sáwọn arìndìn tí wọ́n máa ń ‘tẹ́ńbẹ́lú ọgbọ́n àti ìbáwí?’ (Òwe 1:7) Kí ni àbájáde kíkọ̀ tí wọ́n kọ̀ láti gba ìbáwí látọ̀dọ̀ Jèhófà? Gẹ́gẹ́ bá a ṣe rí i lẹ́ẹ̀kan, Sólómọ́nì sọ pé: “Ìbáwí àwọn òmùgọ̀ sì ni ìwà òmùgọ̀.” (Òwe 16:22) Wọ́n tún ń gba ìbáwí lọ́nà míì o, ó sì sábà máa ń jẹ́ nípa jíjẹ ìyà tó tó ìyà. Àwọn arìndìn tiẹ̀ tún lè fọwọ́ ara wọn ṣe ohun tó máa fa ìnira, ìtìjú, àìsàn tàbí ikú àìtọ́jọ́.
-