ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ṣọ́ra Fún Ọtí Àmujù
    Ilé Ìṣọ́—2004 | December 1
    • 2. Àwọn ìbéèrè wo la óò gbé yẹ̀ wò lórí ọ̀ràn ọtí mímu?

      2 Ìgbà tẹ́nì kan bá lo ẹ̀bùn rere kan bó ṣe tọ́ àti bó ṣe yẹ ló máa tó se onítọ̀hún láǹfààní. Bí àpẹẹrẹ, “oyin” dára àmọ́ “jíjẹ oyin ní àjẹjù kò dára.” (Òwe 24:13; 25:27) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lè má burú téèyàn bá mu “wáìnì díẹ̀,” àmọ́ ìṣòro ńlá ló jẹ́ téèyàn bá ń mu ọtí lámujù. (1 Tímótì 5:23) Bíbélì kìlọ̀ pé: “Afiniṣẹ̀sín ni wáìnì, aláriwo líle ni ọtí tí ń pani, olúkúlùkù ẹni tí ó bá sì tipasẹ̀ rẹ̀ ṣáko lọ kò gbọ́n.” (Òwe 20:1) Àmọ́, tá a bá sọ pé ẹnì kan tipasẹ̀ ọtí “ṣáko lọ,” kí ló túmọ̀ sí?a Kí ni ìwọ̀n ọtí tó pọ̀ jù fún èèyàn láti mu? Ojú wo ló yẹ ká fi wo ọ̀ràn ọtí mímú?

      Báwo Ni Ọtí Ṣe Lè Mú Èèyàn “Ṣáko Lọ”?

      3, 4. (a) Kí ló fi hàn pé ẹ̀ṣẹ̀ ni Bíbélì ka ọtí àmujù sí? (b) Kí ni díẹ̀ lára àwọn ohun téèyàn á fi mọ̀ pé ẹnì kan ti mutí yó?

      3 Láyé ọjọ́un lórílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì, tí ọmọ kan bá jẹ́ alájẹkì àti ọ̀mùtípara tí ọmọ ọ̀hún ò sì ronú pìwà dà, ńṣe ni wọ́n máa sọ ọ́ lókùúta pa. (Diutarónómì 21:18-21) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gba àwọn Kristẹni nímọ̀ràn pé: “Ẹ jáwọ́ dídarapọ̀ nínú ìbákẹ́gbẹ́pọ̀ pẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí a pè ní arákùnrin, tí ó jẹ́ àgbèrè tàbí oníwọra tàbí abọ̀rìṣà tàbí olùkẹ́gàn tàbí ọ̀mùtípara tàbí alọ́nilọ́wọ́gbà, kí ẹ má tilẹ̀ bá irúfẹ́ ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹun.” Ó ṣe kedere pé ẹ̀ṣẹ̀ ni Ìwé Mímọ́ ka ọtí àmujù sí.—1 Kọ́ríńtì 5:11; 6:9, 10.

      4 Nígbà tí Bíbélì ń sọ àwọn ohun téèyàn máa fi mọ̀ pé ẹnì kan ti mutí yó, ó sọ pé: “Má wo wáìnì nígbà tí ó bá yọ àwọ̀ pupa, nígbà tí ó bá ń ta wíríwírí nínú ife, nígbà tí ó bá ń lọ tìnrín. Ní òpin rẹ̀, a buni ṣán gẹ́gẹ́ bí ejò, a sì tu oró jáde gẹ́gẹ́ bí paramọ́lẹ̀. Ojú ìwọ fúnra rẹ yóò rí àwọn ohun àjèjì, ọkàn-àyà rẹ yóò sì sọ àwọn ohun àyídáyidà.” (Òwe 23:31-33) Ńṣe ni ọtí àmujù máa ń buni ṣán bí ejò, ó ń fa àìsàn, ó lè mú kéèyàn máa sọ kántankàntan tàbí kó má tiẹ̀ mọra pàápàá. Ọ̀mùtí lè máa “rí àwọn ohun àjèjì” ní ti pé ó lè máa ṣèrànrán. Ó lè bẹ̀rẹ̀ sí í sọ ìsọkúsọ, kó sì wá máa hùwà tí kò jẹ́ hù ká ní pé kó mutí.

      5. Kí ló mú ọtí àmujù burú?

      5 Tẹ́nì kan bá wá ń mu ọtí bí ẹní mumi àmọ́ tí ò hàn lójú ẹ̀ tàbí kó máa ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ ńkọ́? Àwọn kan wà tó jẹ́ pé bí wọ́n tilẹ̀ mu odidi àgbá pàápàá, kò ní hàn lójú wọn. Ṣùgbọ́n, tẹ́nì kan bá rò pé òun lé máa hu irú ìwà yẹn kóun sì mú un jẹ, ńṣe lonítọ̀hún ń tan ara rẹ̀. (Jeremáyà 17:9) Ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀, ọtí mímu á di bárakú sí i lára, á sì di “ẹrú fún ọ̀pọ̀ wáìnì.” (Títù 2:3) Nígbà tí òǹkọ̀wé nì, Caroline Knapp ń sọ̀rọ̀ nípa béèyàn ṣe ń di ọ̀mùtí, ó ní: “Ọjọ́ kan kọ́ lèèyàn ń di ọ̀mùtí, díẹ̀díẹ̀ ló máa ń bẹ̀rẹ̀, èèyàn ò sì ní mọ̀gbà tó máa wọ̀ ọ́ lẹ́wù.” Ọ̀fìn gbáà ni ọtí àmujù!

      6. Kí nìdí tí kò fi yẹ kéèyàn máa mutí para tàbí kó máa jẹ àjẹkì?

      6 Tún wo ìkìlọ̀ Jésù, ó ní: “Ẹ kíyè sí ara yín, kí ọkàn-àyà yín má bàa di èyí tí a dẹrù pa pẹ̀lú àjẹjù àti ìmutíyó kẹ́ri àti àwọn àníyàn ìgbésí ayé, lójijì tí ọjọ́ yẹn yóò sì dé bá yín ní ìṣẹ́jú akàn gẹ́gẹ́ bí ìdẹkùn. Nítorí yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé ní ojú gbogbo ilẹ̀ ayé.” (Lúùkù 21:34, 35) Kò dìgbà tẹ́nì kan bá ń mutí yó pàápàá kí ọtí tó sọ onítọ̀hún di ọ̀lẹ àti ẹni tó ń tòògbé nípa tara àti nípa tẹ̀mí. Tí ọjọ́ Jèhófà bá wá lọ dé bá irú ẹni bẹ́ẹ̀ nírú ipò yẹn ńkọ́?

  • Ṣọ́ra Fún Ọtí Àmujù
    Ilé Ìṣọ́—2004 | December 1
    • 10. Àkóbá wo ni ọtí lè ṣe fún ọpọlọ wa, kí sì nìdí tí èyí fi léwu?

      10 Kì í ṣe nípa tara nìkan ni ọtí àmujù ti máa ń ṣàkóbá fún èèyàn, ó tún máa ń ṣàkóbá nípa tẹ̀mí pẹ̀lú. Bíbélì sọ pé: “Wáìnì àti wáìnì dídùn ni ohun tí ń gba ète rere kúrò.” (Hóséà 4:11) Ọtí kì í jẹ́ kéèyàn mọ ohun tó ń ṣe nígbà míì. Ìwé kan tí Àjọ Tó Ń Rí sí Ìlòkulò Oògùn ní Orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà kọ sọ pé: “Téèyàn bá ti mutí, ńṣe ni ọtí ọ̀hún máa gba inú òòlọ̀ lọ sínú iṣan àti ẹ̀jẹ̀, kíá ló sì máa dénú ọpọlọ. Kò wá ní jẹ́ kéèyàn ronú dáadáa mọ́, èèyàn ò sì ní fi bẹ́ẹ̀ mọ nǹkan kan lára. Onítọ̀hún ò wá ní lè kó ara rẹ̀ níjàánu.” Tá a bá wà nírú ipò yẹn, a ò ní mọ̀gbà tá a máa ‘ṣáko lọ,’ tí a óò kọjá àyè ara wa, ọ̀pọ̀ ìdẹkùn ló sì máa wá rọ̀gbà yí wa ká.—Òwe 20:1.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́