-
Ṣé O Ti Múra Tán Láti Ṣèrìbọmi?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. Bó o ṣe lè borí àwọn ìṣòro tó lè mú kó nira fún ẹ láti ṣèrìbọmi
Gbogbo wa la máa kojú ìṣòro tá a bá ya ara wa sí mímọ́ fún Jèhófà, tá a sì ṣèrìbọmi. Kó o lè rí àpẹẹrẹ kan, wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Nínú fídíò yẹn, ìṣòro wo ni Narangerel ní láti borí kó lè sin Jèhófà?
Báwo ni ìfẹ́ tó ní fún Jèhófà ṣe ràn án lọ́wọ́ láti borí ìṣòro náà?
Ka Òwe 29:25 àti 2 Tímótì 1:7, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Kí ló máa jẹ́ ká nígboyà ká lè borí àwọn ìṣòro wa?
-
-
O Lè Jẹ́ Adúróṣinṣin sí Jèhófà Táwọn Èèyàn Bá Tiẹ̀ Ń Ta Kò Ẹ́Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
Àsìkò tá a wà yìí ló yẹ ká túbọ̀ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. Rí i pé ò ń wáyè láti máa gbàdúrà sí Jèhófà déédéé, kó o sì máa ka Bíbélì lójoojúmọ́. Máa lọ sí ìpàdé ìjọ déédéé. Àwọn nǹkan yìí á fún ẹ lókun, á sì jẹ́ kó o nígboyà láti kojú inúnibíni tàbí àtakò èyíkéyìí, kódà tó bá jẹ́ pé ìdílé rẹ ló ń ta kò ẹ́. Ọ̀pọ̀ ìgbà làwọn èèyàn ṣenúnibíni sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, ó sọ pé: “Jèhófà ni olùrànlọ́wọ́ mi; mi ò ní bẹ̀rù.”—Hébérù 13:6.
Bákan náà, a máa túbọ̀ jẹ́ onígboyà tá a bá ń wàásù déédéé. Torí ṣe ni iṣẹ́ ìwàásù máa ń jẹ́ ká túbọ̀ gbára lé Jèhófà, ìyẹn ò sì ní jẹ́ ká bẹ̀rù ẹnikẹ́ni. (Òwe 29:25) Tó o bá ti jẹ́ kó mọ́ ẹ lára láti máa fìgboyà wàásù báyìí, ó máa rọrùn fún ẹ láti máa wàásù táwọn ìjọba bá tiẹ̀ pàṣẹ pé a ò gbọ́dọ̀ wàásù.—1 Tẹsalóníkà 2:2.
-