-
Ní Ìbárẹ́ Tímọ́tímọ́ Pẹ̀lú JèhófàIlé Ìṣọ́—2000 | January 15
-
-
Ọlọgbọ́n ọba náà ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ pé: “Fi gbogbo ọkàn-àyà rẹ gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà, má sì gbára lé òye tìrẹ. Ṣàkíyèsí rẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà rẹ, òun fúnra rẹ̀ yóò sì mú àwọn ipa ọ̀nà rẹ tọ́.”—Òwe 3:5, 6.
-
-
Ní Ìbárẹ́ Tímọ́tímọ́ Pẹ̀lú JèhófàIlé Ìṣọ́—2000 | January 15
-
-
Báwo la ṣe lè ‘kíyè sí Jèhófà ní gbogbo ọ̀nà wa’? Onísáàmù tí a mí sí náà sọ pé: “Dájúdájú, èmi yóò máa ṣe àṣàrò lórí gbogbo ìgbòkègbodò rẹ, ṣe ni èmi yóò sì máa dàníyàn nípa ìbálò rẹ.” (Sáàmù 77:12) Níwọ̀n bí a kò ti lè fojú rí Ọlọ́run, ṣíṣàṣàrò lórí àwọn iṣẹ́ arabarìbì rẹ̀ àti lórí bí ó ṣe bá àwọn ènìyàn rẹ̀ lò ṣe pàtàkì fún wa láti ní ìbárẹ́ tímọ́tímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Àdúrà tún jẹ́ ọ̀nà pàtàkì láti kíyè sí Jèhófà. Dáfídì Ọba ń ké pe Jèhófà “láti òwúrọ̀ ṣúlẹ̀.” (Sáàmù 86:3) Nígbà mìíràn, Dáfídì máa ń gbàdúrà ní gbogbo òru, bí irú ìgbà tó jẹ́ ìsáǹsá nínú aginjù. (Sáàmù 63:6, 7) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù gbani níyànjú pé: “Ẹ máa bá a lọ ní gbígbàdúrà ní gbogbo ìgbà nínú ẹ̀mí.” (Éfésù 6:18) Báwo la ṣe máa ń gbàdúrà léraléra tó? Ǹjẹ́ a máa ń gbádùn bíbá Ọlọ́run sọ̀rọ̀ látọkànwá? Nígbà tí a bá dojú kọ àwọn ipò líle koko, ǹjẹ́ a máa ń bẹ̀ ẹ́ fún ìrànlọ́wọ́? Ǹjẹ́ a máa ń fi tàdúràtàdúrà béèrè ìdarí rẹ̀ kí a tó ṣe àwọn ìpinnu tó ṣe pàtàkì? Àwọn àdúrà àtọkànwá táa bá gbà sí Jèhófà ń fà wá sún mọ́ ọn. A sì ní ìdánilójú pé yóò gbọ́ àdúrà wa, yóò sì ‘mú ọ̀nà wa tọ́.’
-