-
Bá A Ṣe Lè Ṣe Ìpinnu Tó DáaGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. Bọ̀wọ̀ fún ẹ̀rí ọkàn àwọn ẹlòmíì
Ìpinnu wa máa ń yàtọ̀ síra. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a bọ̀wọ̀ fún ẹ̀rí ọkàn àwọn ẹlòmíì? Jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ méjì yìí:
Àpẹẹrẹ àkọ́kọ́: Arábìnrin kan fẹ́ràn kó máa tọ́jú tọ́tè. Àmọ́, ó wá kó lọ sí àdúgbò míì táwọn ará ò ti gbà pé ó bójú mu kéèyàn máa tọ́jú tọ́tè.
Ka Róòmù 15:1 àti 1 Kọ́ríńtì 10:23, 24, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Pẹ̀lú ohun tó wà nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí, kí ni arábìnrin yẹn lè ṣe? Ká sọ pé o fẹ́ ṣe ohun kan tí kò da ẹ̀rí ọkàn ẹ láàmú, àmọ́ tó ń da ẹ̀rí ọkàn ẹlòmíì láàmú, kí ni wàá ṣe?
Àpẹẹrẹ kejì: Arákùnrin kan mọ̀ pé Bíbélì ò sọ pé kéèyàn má mu ọtí, tó bá ṣáà ti jẹ́ níwọ̀nba. Àmọ́ arákùnrin yìí ti pinnu pé òun ò ní máa mu ọtí. Wọ́n wá pè é síbi àpèjẹ kan tí àwọn ará ti ń mu ọtí.
Ka Oníwàásù 7:16 àti Róòmù 14:1, 10, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Pẹ̀lú ohun tó wà nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí, kí ni kò yẹ kí arákùnrin yẹn ṣe? Kí lo máa ṣe tó o bá rí i pé ẹnì kan ń ṣe ohun kan tí kò bá ẹ̀rí ọkàn tìẹ mu?
Bó o ṣe lè ṣe ìpinnu tó dáa
1. Gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ràn ẹ́ lọ́wọ́ kó o lè mọ ohun tó yẹ kó o ṣe.—Jémíìsì 1:5.
2. Ṣe ìwádìí nínú Bíbélì àtàwọn ìwé àti fídíò tó ń ṣàlàyé Bíbélì. O tún lè fọ̀rọ̀ náà lọ àwọn arákùnrin àti arábìnrin tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn.
3. Máa ro ìgbẹ̀yìn ọ̀rọ̀ tó o bá ń ṣèpinnu. Ronú nípa àkóbá tó lè ṣe fún ẹ, kó o sì wò ó bóyá kò ní da ẹ̀rí ọkàn àwọn míì láàmú.
-
-
Báwo La Ṣe Lè Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Tá À Ń Sọ Múnú Jèhófà Dùn?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. Máa sọ ohun tó dáa nípa àwọn míì
Kí la lè ṣe tá ò fi ní máa bú àwọn èèyàn tàbí sọ ohun tó máa kó ẹ̀dùn ọkàn bá wọn? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Nínú fídíò yẹn, kí nìdí tí arákùnrin yẹn fi ronú pé á dáa kóun ṣàtúnṣe lórí bó ṣe ń bá àwọn míì sọ̀rọ̀?
Àwọn nǹkan wo ló ṣe kí ọ̀rọ̀ ẹ̀ lè máa tu àwọn míì lára?
Ka Oníwàásù 7:16, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Kí ló yẹ ká fi sọ́kàn tó bá ń ṣe wá bíi pé ká sọ ohun tí ò dáa nípa ẹnì kan?
Ka Oníwàásù 7:21, 22, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Báwo ni ẹsẹ Bíbélì yìí ṣe lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ kó o má bàa bínú sódì tẹ́nì kan bá sọ ohun tí ò dáa nípa rẹ?
-