ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Bá A Ṣe Lè Ṣe Ìpinnu Tó Dáa
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 5. Bọ̀wọ̀ fún ẹ̀rí ọkàn àwọn ẹlòmíì

      Ìpinnu wa máa ń yàtọ̀ síra. Báwo la ṣe lè fi hàn pé a bọ̀wọ̀ fún ẹ̀rí ọkàn àwọn ẹlòmíì? Jẹ́ ká wo àpẹẹrẹ méjì yìí:

      Àpẹẹrẹ àkọ́kọ́: Arábìnrin kan fẹ́ràn kó máa tọ́jú tọ́tè. Àmọ́, ó wá kó lọ sí àdúgbò míì táwọn ará ò ti gbà pé ó bójú mu kéèyàn máa tọ́jú tọ́tè.

      Ka Róòmù 15:1 àti 1 Kọ́ríńtì 10:23, 24, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

      • Pẹ̀lú ohun tó wà nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí, kí ni arábìnrin yẹn lè ṣe? Ká sọ pé o fẹ́ ṣe ohun kan tí kò da ẹ̀rí ọkàn ẹ láàmú, àmọ́ tó ń da ẹ̀rí ọkàn ẹlòmíì láàmú, kí ni wàá ṣe?

      Àpẹẹrẹ kejì: Arákùnrin kan mọ̀ pé Bíbélì ò sọ pé kéèyàn má mu ọtí, tó bá ṣáà ti jẹ́ níwọ̀nba. Àmọ́ arákùnrin yìí ti pinnu pé òun ò ní máa mu ọtí. Wọ́n wá pè é síbi àpèjẹ kan tí àwọn ará ti ń mu ọtí.

      Ka Oníwàásù 7:16 àti Róòmù 14:1, 10, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:

      • Pẹ̀lú ohun tó wà nínú àwọn ẹsẹ Bíbélì yìí, kí ni kò yẹ kí arákùnrin yẹn ṣe? Kí lo máa ṣe tó o bá rí i pé ẹnì kan ń ṣe ohun kan tí kò bá ẹ̀rí ọkàn tìẹ mu?

      Bó o ṣe lè ṣe ìpinnu tó dáa

      Obìnrin kan ń gbàdúrà.

      1. Gbàdúrà sí Jèhófà pé kó ràn ẹ́ lọ́wọ́ kó o lè mọ ohun tó yẹ kó o ṣe.​—Jémíìsì 1:5.

      Obìnrin náà ń ṣèwádìí. Ó lo Bíbélì àtàwọn ìwé tó ń ṣàlàyé Bíbélì, ó sì tún ń lo kọ̀ǹpútà.

      2. Ṣe ìwádìí nínú Bíbélì àtàwọn ìwé àti fídíò tó ń ṣàlàyé Bíbélì. O tún lè fọ̀rọ̀ náà lọ àwọn arákùnrin àti arábìnrin tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn.

      Obìnrin náà ń ronú jinlẹ̀.

      3. Máa ro ìgbẹ̀yìn ọ̀rọ̀ tó o bá ń ṣèpinnu. Ronú nípa àkóbá tó lè ṣe fún ẹ, kó o sì wò ó bóyá kò ní da ẹ̀rí ọkàn àwọn míì láàmú.

  • Báwo La Ṣe Lè Jẹ́ Kí Ọ̀rọ̀ Tá À Ń Sọ Múnú Jèhófà Dùn?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 5. Máa sọ ohun tó dáa nípa àwọn míì

      Kí la lè ṣe tá ò fi ní máa bú àwọn èèyàn tàbí sọ ohun tó máa kó ẹ̀dùn ọkàn bá wọn? Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.

      FÍDÍÒ: Máa Sọ “Ọ̀rọ̀ Tó Ń Gbéni Ró” Fáwọn Míì (4:07)

      • Nínú fídíò yẹn, kí nìdí tí arákùnrin yẹn fi ronú pé á dáa kóun ṣàtúnṣe lórí bó ṣe ń bá àwọn míì sọ̀rọ̀?

      • Àwọn nǹkan wo ló ṣe kí ọ̀rọ̀ ẹ̀ lè máa tu àwọn míì lára?

      Ka Oníwàásù 7:16, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

      • Kí ló yẹ ká fi sọ́kàn tó bá ń ṣe wá bíi pé ká sọ ohun tí ò dáa nípa ẹnì kan?

      Ka Oníwàásù 7:21, 22, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:

      • Báwo ni ẹsẹ Bíbélì yìí ṣe lè ràn ẹ́ lọ́wọ́ kó o má bàa bínú sódì tẹ́nì kan bá sọ ohun tí ò dáa nípa rẹ?

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́