- 
	                        
            
            Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Orin Sólómọ́nìIlé Ìṣọ́—2006 | November 15
- 
                            - 
                                        2:7; 3:5—Kí nìdí tó fi fi àwọn ọmọbìnrin tó wà láàfin sábẹ́ ìbúra “nípasẹ̀ àwọn abo àgbàlàǹgbó tàbí nípasẹ̀ àwọn egbin inú pápá”? Àwọn àgbàlàǹgbó àti egbin máa ń wuni wò nítorí ìrìn ẹ̀yẹ àti ẹwà wọn. Nítorí náà, ńṣe ni omidan Ṣúlámáítì ń lo gbogbo ohun yòówù tó bá rẹwà tó sì dára láti fi àwọn ọmọbìnrin tó wà láàfin sábẹ́ ìbúra pé kí wọ́n má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ wá sóun lọ́kàn. 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Orin Sólómọ́nìIlé Ìṣọ́—2006 | November 15
- 
                            - 
                                        2:7; 3:5. Ọkàn ọmọbìnrin tó ti ìgbèríko wá yìí ò fi ibì kankan fà sí Sólómọ́nì. Ó tún fi àwọn ọmọbìnrin tó wà láàfin ọba sábẹ́ ìbúra pé kí wọ́n má ṣe ru ìfẹ́ sókè nínú òun fún ẹnikẹ́ni yàtọ̀ sí ọ̀dọ́mọkùnrin olùṣọ́ àgùntàn náà. Ọkàn èèyàn ò lè ṣàdédé máa fà sí ẹlòmíì láìnídìí, bẹ́ẹ̀ ni kò sì yẹ kó rí bẹ́ẹ̀. Ìránṣẹ́ Jèhófà tó jẹ́ adúróṣinṣin nìkan ló yẹ kó wu Kristẹni àpọ́n tó ń gbèrò àtiṣègbéyàwó láti fẹ́.—1 Kọ́ríńtì 7:39. 
 
-