-
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Orin Sólómọ́nìIlé Ìṣọ́—2006 | November 15
-
-
1:2, 3—Kí nìdí tí rírántí àwọn ìfìfẹ́hàn ọ̀dọ́mọkùnrin olùṣọ́ àgùntàn náà fi dà bíi wáìnì tí orúkọ rẹ̀ sì dà bí òróró? Bí wáìnì ṣe máa ń mú ọkàn èèyàn yọ̀ àti bí ara ṣe máa ń tuni bí wọ́n bá da òróró síni lórí, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe jẹ́ pé bí omidan yìí bá ṣe ń rántí ìfẹ́ ọmọkùnrin yìí àti orúkọ rẹ̀, ṣe ló máa ń fún un lókun tó sì máa ń tù ú nínú. (Sáàmù 23:5; 104:15) Bákan náà ló ṣe jẹ́ pé báwọn Kristẹni tòótọ́, pàápàá àwọn ẹni àmì òróró, ṣe ń ronú lórí ìfẹ́ tí Jésù Kristi ti fi hàn sí wọn, ó ń sọ agbára wọn dọ̀tun ó sì ń fún wọn níṣìírí.
-
-
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Orin Sólómọ́nìIlé Ìṣọ́—2006 | November 15
-
-
1:2; 2:6. Fífi ìfẹ́ hàn síra ẹni lè jẹ́ ohun tó bójú mu bí tọkùnrin tobìnrin bá ń fẹ́ra wọn sọ́nà. Àmọ́, àwọn méjèèjì gbọ́dọ̀ kíyè sára kó bàa lè jẹ́ pé ìfẹ́ tó dénú ni wọ́n ń fi hàn síra wọn, kì í ṣe ìfẹ́ onígbòónára, èyí tó lè mú kí wọ́n bára wọn ṣèṣekúṣe.—Gálátíà 5:19.
-