-
“Ẹ Tu Àwọn Ènìyàn Mi Nínú”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
14. (a) Báwo ni Aísáyà ṣe ṣàpèjúwe ọ̀nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́ tí Jèhófà yóò gbà ṣamọ̀nà àwọn èèyàn rẹ̀? (b) Àpẹẹrẹ wo ló fi ọ̀nà tí àwọn olùṣọ́ àgùntàn gbà ń ṣìkẹ́ àwọn àgùntàn wọn hàn? (Wo àpótí ojú ewé 405.)
14 Àmọ́ ṣá o, Ọlọ́run alágbára yìí tún ní ọwọ́ jẹ̀lẹ́ńkẹ́ o. Aísáyà fi ìdùnnú ṣàpèjúwe bí Jèhófà yóò ṣe ṣamọ̀nà àwọn èèyàn rẹ̀ padà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn. Ńṣe ni Jèhófà dà bí olùṣọ́ àgùntàn onífẹ̀ẹ́ tó kó àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn rẹ̀ jọ, tó sì kó wọn sí “oókan àyà” rẹ̀. Ó dájú pé ìṣẹ́po ẹ̀wù lápá òkè ni ọ̀rọ̀ náà “oókan àyà” ń tọ́ka sí níhìn-ín. Nígbà mìíràn, ibẹ̀ làwọn olùṣọ́ àgùntàn máa ń gbé àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn àṣẹ̀ṣẹ̀bí sí, tí kò bá lè kọ́wọ̀ọ́rìn pẹ̀lú agbo. (2 Sámúẹ́lì 12:3) Láìsí àní-àní, irú ìran tó wúni lórí bẹ́ẹ̀, látinú ohun táwọn darandaran máa ń ṣe láti ọjọ́ dé ọjọ́, fi ọkàn àwọn èèyàn Jèhófà tó wà nígbèkùn balẹ̀ pé ó ń fi tìfẹ́tìfẹ́ kọbi ara sí ọ̀ràn àwọn. Dájúdájú, irú Ọlọ́run alágbára tó tún jẹ́ oníkẹ̀ẹ́ bẹ́ẹ̀ mà ṣeé gbẹ́kẹ̀ lé o, pé yóò mú ohun tó ṣèlérí fún wọn ṣẹ!
-
-
“Ẹ Tu Àwọn Ènìyàn Mi Nínú”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
16. Irú ọwọ́ wo ni Jèhófà fi ń ṣamọ̀nà àwọn èèyàn rẹ̀ lóde òní, èyí sì jẹ́ àwòkọ́ṣe fún àwọn wo?
16 Ọ̀rọ̀ inú Aísáyà 40:10, 11 tún wúlò síwájú sí i fún wa lóde òní. Ìtùnú ló jẹ́ fúnni láti ri bí Jèhófà ṣe ń fi ọwọ́ jẹ̀lẹ́ńkẹ́ ṣamọ̀nà àwọn èèyàn rẹ̀. Gẹ́lẹ́ bí olùṣọ́ àgùntàn ṣe mọ àìní àgùntàn kọ̀ọ̀kan, àní títí kan àwọn ọ̀dọ̀ àgùntàn lẹ̀jẹ́lẹ̀jẹ́ tí kò lè kọ́wọ̀ọ́rìn pẹ̀lú ìyókù agbo, ni Jèhófà ṣe mọ ibi tí agbára olúkúlùkù ìránṣẹ́ rẹ̀ olóòótọ́ mọ. Ẹ̀wẹ̀, jíjẹ́ tí Jèhófà jẹ́ Olùṣọ́ Àgùntàn oníkẹ̀ẹ́ yìí jẹ́ àwòkọ́ṣe fún àwọn Kristẹni olùṣọ́ àgùntàn. Ọwọ́ jẹ̀lẹ́ńkẹ́ ni àwọn alàgbà gbọ́dọ̀ fi mú agbo, kí wọ́n ṣàfarawé àfiyèsí onífẹ̀ẹ́ tí Jèhófà fúnra rẹ̀ ń fi hàn. Kí wọ́n máa fi bí ọ̀ràn ẹnì kọ̀ọ̀kan tó wà nínú agbo ṣe rí lára Jèhófà sọ́kàn nígbà gbogbo, agbo “tí ó fi ẹ̀jẹ̀ Ọmọ òun fúnra rẹ̀ rà.”—Ìṣe 20:28.
-
-
“Ẹ Tu Àwọn Ènìyàn Mi Nínú”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
[Àpótí/Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 405]
Jèhófà, Olùṣọ́ Àgùntàn Onífẹ̀ẹ́
Aísáyà fi Jèhófà wé olùṣọ́ àgùntàn onífẹ̀ẹ́ tó máa ń gbé àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn rẹ̀ sí oókan àyà rẹ̀. (Aísáyà 40:10, 11) Ó dájú pé ohun tí àwọn olùṣọ́ àgùntàn máa ń ṣe láti ọjọ́ dé ọjọ́ ni Aísáyà lò nínú àpẹẹrẹ tó fani mọ́ra yìí. Alákìíyèsí kan láyé òde òní, tó kíyè sí bí àwọn olùṣọ́ àgùntàn ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Òkè Hámónì ní Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ayé ṣe máa ń ṣe, ròyìn pé: “Ńṣe ni olùṣọ́ àgùntàn kọ̀ọ̀kan máa ń ṣọ́ agbo tirẹ̀ lójú méjèèjì láti lè mọ bí wọ́n ti ń ṣe sí. Tó bá wá rí àṣẹ̀ṣẹ̀bí ọ̀dọ́ àgùntàn, inú ìṣẹ́po . . . ẹ̀wù àwọ̀lékè rẹ̀ ló máa ń gbé e sí, nítorí pé kò tíì lè lágbára tó láti lè tọ ìyá rẹ̀ lẹ́yìn. Bó bá di pé oókan àyà rẹ̀ kún, a máa gbé ọ̀dọ́ àgùntàn sí èjìká, tí yóò dì wọ́n mú ní ẹsẹ̀, tàbí kó fi àpò tàbí apẹ̀rẹ̀ gbé wọn sẹ́yìn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, títí àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn lẹ̀jẹ́lẹ̀jẹ́ yẹn yóò fi lè kọ́wọ̀ọ́rìn pẹ̀lú ìyá wọn.” Kò ha tuni nínú láti mọ̀ pé irú Ọlọ́run tó ń ṣìkẹ́ àwọn èèyàn rẹ̀ bẹ́ẹ̀ là ń sìn?
-