ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Àyànfẹ́ Mi, Ẹni Tí Ọkàn Mi Tẹ́wọ́ Gbà!”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 3. Kí ni Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀ nípa “ìránṣẹ́ mi”?

      3 Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìránṣẹ́ kan tóun yóò fúnra òun yàn, ó ní: “Wò ó! Ìránṣẹ́ mi, tí mo dì mú ṣinṣin! Àyànfẹ́ mi, ẹni tí ọkàn mi tẹ́wọ́ gbà! Èmi ti fi ẹ̀mí mi sára rẹ̀. Ìdájọ́ òdodo fún àwọn orílẹ̀-èdè ni ohun tí yóò mú wá. Kì yóò ké jáde tàbí kí ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, kì yóò sì jẹ́ kí a gbọ́ ohùn òun ní ojú pópó. Kò sí esùsú fífọ́ tí òun yóò ṣẹ́; àti ní ti òwú àtùpà tí a fi ọ̀gbọ̀ ṣe tí ń jó bàìbàì, òun kì yóò fẹ́ ẹ pa. Nínú òótọ́ ni òun yóò mú ìdájọ́ òdodo wá. Òun kì yóò di bàìbàì, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò tẹ̀ ẹ́ rẹ́ títí yóò fi gbé ìdájọ́ òdodo kalẹ̀ ní ilẹ̀ ayé; òfin rẹ̀ sì ni àwọn erékùṣù pàápàá yóò máa dúró dè.”—Aísáyà 42:1-4.

  • “Àyànfẹ́ Mi, Ẹni Tí Ọkàn Mi Tẹ́wọ́ Gbà!”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 6. Ní àwọn ọ̀nà wo ni Jésù gbà mú kí ìdájọ́ òdodo tòótọ́ di mímọ̀?

      6 Jésù kò dà bíi tiwọn ṣá, ó fi èrò Ọlọ́run nípa ìdájọ́ òdodo hàn. Ní ọ̀nà tí Jésù gbà kọ́ni àti bó ṣe gbé ìgbé ayé rẹ̀, ó fi hàn pé ìdájọ́ òdodo tòótọ́ ní ìyọ́nú àti àánú nínú. Ẹ sáà tiẹ̀ gbé Ìwàásù Lórí Òkè tó ṣe yẹ̀ wò. (Mátíù, orí karùn-ún sí ìkeje) Àgbà àlàyé nípa bó ṣe yẹ kéèyàn ṣe ìdájọ́ òdodo àti òdodo mà nìyẹn o! Nígbà tí a bá ka àwọn ìtàn inú Ìhìn Rere, ǹjẹ́ bí Jésù ṣe fi ìyọ́nú hàn sí àwọn tálákà àti àwọn tí ìyà ń jẹ kì í wú wa lórí? (Mátíù 20:34; Máàkù 1:41; 6:34; Lúùkù 7:13) Ó mú ìhìn ìtùnú rẹ̀ dé ọ̀dọ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn tó dà bí esùsú fífọ́ tó ti ṣẹ́po tí a sì ń gbá káàkiri. Wọ́n dà bí òwú àtùpà tí a fi ọ̀gbọ̀ ṣe tó ń jó lọ́úlọ́ú, tí ẹ̀ṣẹ́ná ìkẹyìn tó kù fún wọn ní ìgbésí ayé sì ti fẹ́rẹ̀ẹ́ kú. Jésù kò ṣẹ́ “esùsú fífọ́” kankan bẹ́ẹ̀ ni kò sì fẹ́ “òwú àtùpà tí a fi ọ̀gbọ̀ ṣe tí ń jó bàìbàì” kankan pa. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni ọ̀rọ̀ àti ìṣe rẹ̀ onífẹ̀ẹ́ àti oníyọ̀ọ́nú ń tu àwọn ọlọ́kàn tútù nínú.—Mátíù 11:28-30.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́