-
Ta Ni Ọlọ́run?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
1. Kí ni orúkọ Ọlọ́run, báwo la sì ṣe mọ̀ pé ó fẹ́ ká mọ orúkọ náà?
Ọlọ́run sọ orúkọ ara ẹ̀ fún wa nínú Bíbélì. Ó ní: “Èmi ni Jèhófà. Orúkọ mi nìyẹn.” (Ka Àìsáyà 42:5, 8.) Orúkọ náà “Jèhófà” wá látinú èdè Hébérù tí ẹ̀rí fi hàn pé ó túmọ̀ sí “Ó Ń Mú Kí Ó Di.” Jèhófà fẹ́ ká mọ orúkọ rẹ̀ yìí. (Ẹ́kísódù 3:15) Báwo la ṣe mọ̀ bẹ́ẹ̀? Ó lé ní ẹgbẹ̀rún méje (7,000) ìgbà tí orúkọ Ọlọ́run fara hàn nínú Bíbélì!a “Ọlọ́run tòótọ́ lókè ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé” nìkan ló ń jẹ́ orúkọ náà Jèhófà.—Diutarónómì 4:39.
-
-
Báwo La Ṣe Lè Mọ Ìjọsìn Tí Ọlọ́run Tẹ́wọ́ Gbà?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
2. Báwo ló ṣe yẹ ká máa jọ́sìn Jèhófà?
Nítorí pé Jèhófà ni Ẹlẹ́dàá wa, a ò gbọ́dọ̀ mú nǹkan míì mọ́ ìjọsìn rẹ̀. (Ìfihàn 4:11) Ìyẹn ni pé a gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, ká máa sin òun nìkan ṣoṣo, ká má ṣe sin òrìṣà èyíkéyìí, ká má sì lo ère nínú ìjọsìn wa.—Ka Àìsáyà 42:8.
Ìjọsìn wa gbọ́dọ̀ jẹ́ ‘mímọ́, kó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà’ lójú Jèhófà. (Róòmù 12:1) Ìyẹn ni pé a gbọ́dọ̀ máa gbé ìgbé ayé wa lọ́nà tó bá àwọn ìlànà rẹ̀ mu. Bí àpẹẹrẹ, àwọn tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà máa ń nífẹ̀ẹ́ ìlànà rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ ìgbéyàwó, wọ́n sì máa ń tẹ̀ lé e. Wọn kì í ṣe ohun tó máa pa wọ́n lára, irú bíi mímu sìgá, mímu igbó, fífín tábà tàbí aáṣà, lílo oògùn olóró tàbí mímu ọtí lámujù.a
-