ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ta Ni Ọlọ́run?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 1. Kí ni orúkọ Ọlọ́run, báwo la sì ṣe mọ̀ pé ó fẹ́ ká mọ orúkọ náà?

      Ọlọ́run sọ orúkọ ara ẹ̀ fún wa nínú Bíbélì. Ó ní: “Èmi ni Jèhófà. Orúkọ mi nìyẹn.” (Ka Àìsáyà 42:5, 8.) Orúkọ náà “Jèhófà” wá látinú èdè Hébérù tí ẹ̀rí fi hàn pé ó túmọ̀ sí “Ó Ń Mú Kí Ó Di.” Jèhófà fẹ́ ká mọ orúkọ rẹ̀ yìí. (Ẹ́kísódù 3:15) Báwo la ṣe mọ̀ bẹ́ẹ̀? Ó lé ní ẹgbẹ̀rún méje (7,000) ìgbà tí orúkọ Ọlọ́run fara hàn nínú Bíbélì!a “Ọlọ́run tòótọ́ lókè ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé” nìkan ló ń jẹ́ orúkọ náà Jèhófà.​—Diutarónómì 4:39.

  • Báwo La Ṣe Lè Mọ Ìjọsìn Tí Ọlọ́run Tẹ́wọ́ Gbà?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
    • 2. Báwo ló ṣe yẹ ká máa jọ́sìn Jèhófà?

      Nítorí pé Jèhófà ni Ẹlẹ́dàá wa, a ò gbọ́dọ̀ mú nǹkan míì mọ́ ìjọsìn rẹ̀. (Ìfihàn 4:11) Ìyẹn ni pé a gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, ká máa sin òun nìkan ṣoṣo, ká má ṣe sin òrìṣà èyíkéyìí, ká má sì lo ère nínú ìjọsìn wa.​—Ka Àìsáyà 42:8.

      Ìjọsìn wa gbọ́dọ̀ jẹ́ ‘mímọ́, kó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà’ lójú Jèhófà. (Róòmù 12:1) Ìyẹn ni pé a gbọ́dọ̀ máa gbé ìgbé ayé wa lọ́nà tó bá àwọn ìlànà rẹ̀ mu. Bí àpẹẹrẹ, àwọn tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà máa ń nífẹ̀ẹ́ ìlànà rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ ìgbéyàwó, wọ́n sì máa ń tẹ̀ lé e. Wọn kì í ṣe ohun tó máa pa wọ́n lára, irú bíi mímu sìgá, mímu igbó, fífín tábà tàbí aáṣà, lílo oògùn olóró tàbí mímu ọtí lámujù.a

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́