ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọlọ́run Tòótọ́ Sọ Àsọtẹ́lẹ̀ Ìdáǹdè
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 19, 20. (a) Ọ̀nà wo ni Jèhófà gbà sọ àsọkágbá ọ̀rọ̀ ẹjọ́ rẹ̀? (b) Àwọn ohun amọ́kànyọ̀ wo ni Jèhófà sọ tẹ́lẹ̀ fún àwọn èèyàn rẹ̀, ta sì ni ońṣẹ́ rẹ̀ tí yóò lò láti ṣe àwọn ohun náà?

      19 Jèhófà wá fẹ́ sọ àgbà ọ̀rọ̀ àsọkágbá lórí ẹjọ́ rẹ̀ wàyí. Ó fẹ́ sọ ìdáhùn rẹ̀ lórí ìdánwò tó gbóná jù lọ nípa ẹni tó jẹ́ Ọlọ́run lóòótọ́, ìyẹn agbára láti lè sọ àsọtẹ́lẹ̀ ọjọ́ ọ̀la láìsí pé ó yingin. Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì jinlẹ̀ kan pe ẹsẹ márùn-ún tó tẹ̀ lé e nínú Aísáyà orí kẹrìnlélógójì ní “ewì tó fi Ọlọ́run Ísírẹ́lì hàn bí ẹni gíga jù lọ,” ọ̀kan ṣoṣo Ẹlẹ́dàá, Olùṣípayá ọjọ́ ọ̀la, ìrètí ìdáǹdè fún Ísírẹ́lì. Àyọkà yìí ń rinlẹ̀ síwájú sí i ni látorí àgbà ọ̀rọ̀ kan bọ́ sórí òmíràn títí ó fi dé paríparì rẹ̀ tó ti dárúkọ ẹni tí yóò dá orílẹ̀-èdè yẹn nídè kúrò ní Bábílónì.

      20 Ó ní: “Èyí ni ohun tí Jèhófà wí, Olùtúnnirà rẹ àti Aṣẹ̀dá rẹ láti inú ikùn wá: ‘Èmi, Jèhófà, ń ṣe ohun gbogbo, mo na ọ̀run ní èmi nìkan, mo tẹ́ ilẹ̀ ayé. Ta ni ó wà pẹ̀lú mi? Mo ń mú àwọn iṣẹ́ àmì àwọn olùsọ òfìfo ọ̀rọ̀ já sí pàbó, èmi sì ni Ẹni tí ń mú kí àwọn woṣẹ́woṣẹ́ pàápàá máa ṣe bí ayírí; Ẹni tí ń dá àwọn ọlọ́gbọ́n padà sẹ́yìn, àti Ẹni tí ń sọ ìmọ̀ wọn pàápàá di òmùgọ̀; Ẹni tí ń mú kí ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ ṣẹ, àti Ẹni tí ń mú ìmọ̀ràn àwọn ońṣẹ́ rẹ̀ ṣẹ pátápátá; Ẹni tí ń wí nípa Jerúsálẹ́mù pé, “A óò gbé inú rẹ̀,” àti nípa àwọn ìlú ńlá Júdà pé, “A óò tún wọn kọ́, èmi yóò sì gbé àwọn ibi ahoro rẹ̀ dìde”; Ẹni tí ń wí fún ibú omi pé, “Gbẹ; gbogbo odò rẹ sì ni èmi yóò mú gbẹ táútáú”; Ẹni tí ó wí nípa Kírúsì pé, “Òun ni olùṣọ́ àgùntàn mi, gbogbo ohun tí mo sì ní inú dídùn sí ni òun yóò mú ṣe pátápátá”; àní nínú àsọjáde mi nípa Jerúsálẹ́mù pé, “A óò tún un kọ́,” àti nípa tẹ́ńpìlì pé, “A ó fi ìpìlẹ̀ rẹ lélẹ̀.”’ ”—Aísáyà 44:24-28.

  • Ọlọ́run Tòótọ́ Sọ Àsọtẹ́lẹ̀ Ìdáǹdè
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 22. Ṣàpèjúwe bí Odò Yúfírétì ṣe gbẹ.

      22 Àwọn woṣẹ́woṣẹ́ aláìní ìmísí kì í sọ kúlẹ̀kúlẹ̀ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ ní ṣàkó torí ìbẹ̀rù pé ìgbà lè yí padà kó sì sọ wọ́n dèké. Láìdàbí tiwọn, Jèhófà gbẹnu Aísáyà dárúkọ ẹni tí òun yóò lò láti dá àwọn èèyàn òun nídè kúrò nígbèkùn, tí wọn yóò fi lè padà lọ sílé láti tún Jerúsálẹ́mù àti tẹ́ńpìlì rẹ̀ kọ́. Kírúsì lorúkọ rẹ̀, ayé sì mọ̀ ọ́n sí Kírúsì Ńlá ti Páṣíà. Jèhófà tún sọ kúlẹ̀kúlẹ̀ ọgbọ́n ogun tí Kírúsì yóò dá láti fi jágbọ́n onírúurú ààbò rẹpẹtẹ tó díjú tí Bábílónì gbé kalẹ̀. Àwọn odi tó ga àti àwọn ipadò tó ń ṣàn gba inú ìlú, tó sì tún yí ìlú po, ni Bábílónì yóò fi ṣe ààbò. Ohun tó gba iwájú jù lọ nínú ìgbékalẹ̀ ààbò yìí gan-an ni Kírúsì yóò sì kúkú wá lò láti fi ṣọṣẹ́, ìyẹn Odò Yúfírétì. Gẹ́gẹ́ bí òpìtàn ìgbàanì, Hẹrodótù àti Sẹ́nófọ̀n ṣe wí, ibì kan lápá òkè ibi tí odò yìí ti ń ṣàn wá sí Bábílónì ni Kírúsì ti darí omi odò Yúfírétì gba ibòmíràn lọ, tí omi odò yìí sì fi fà, débi pé àwọn ọmọ ogun rẹ̀ lè wọ́dò kọjá. Nígbà tí odò yìí kò sì ti lè dáàbò bo Bábílónì, alagbalúgbú odò Yúfírétì gbẹ lọ́nà yẹn nìyẹn.

      23. Àkọsílẹ̀ wo ló wà ní ti ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ náà pé Kírúsì yóò dá Ísírẹ́lì nídè?

      23 Ìlérí pé Kírúsì yóò dá àwọn èèyàn Ọlọ́run nídè, pé yóò sì rí sí i pé wọ́n tún Jerúsálẹ́mù àti tẹ́ńpìlì rẹ̀ kọ́ wá ńkọ́? Nínú ìkéde kan tí Kírúsì ọba fúnra rẹ̀ ṣe, tó ṣì wà nínú Bíbélì di báyìí, ó ní: “Èyí ni ohun tí Kírúsì ọba Páṣíà wí, ‘Gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé ni Jèhófà Ọlọ́run ọ̀run ti fi fún mi, òun fúnra rẹ̀ sì ti fàṣẹ yàn mí pé kí n kọ́ ilé fún òun ní Jerúsálẹ́mù, tí ó wà ní Júdà. Ẹnì yòówù tí ń bẹ láàárín yín nínú gbogbo ènìyàn rẹ̀, kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀. Nítorí náà, kí ó gòkè lọ sí Jerúsálẹ́mù, tí ó wà ní Júdà, kí ó sì tún ilé Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì kọ́—òun ni Ọlọ́run tòótọ́—èyí tí ó wà ní Jerúsálẹ́mù.’” (Ẹ́sírà 1:2, 3) Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ ṣẹ látòkèdélẹ̀!

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́