ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jèhófà—“Ọlọ́run Òdodo àti Olùgbàlà”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 3. Àwọn gbólóhùn tó yéni kedere wo ni Aísáyà 45:1-3a fi ṣàpèjúwe ìṣẹ́gun Kírúsì?

      3 Ó ní: “Èyí ni ohun tí Jèhófà wí fún ẹni àmì òróró rẹ̀, fún Kírúsì, ẹni tí mo di ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ mú, láti tẹ àwọn orílẹ̀-èdè lórí ba níwájú rẹ̀, kí n lè tú àmùrè ìgbáròkó àwọn ọba pàápàá; láti ṣí àwọn ilẹ̀kùn aláwẹ́ méjì níwájú rẹ̀, tí yóò fi jẹ́ pé, àwọn ẹnubodè pàápàá ni a kì yóò tì: ‘Èmi fúnra mi yóò lọ níwájú rẹ, èmi yóò sì mú àwọn ìyọgọnbu ilẹ̀ tẹ́jú. Àwọn ilẹ̀kùn bàbà ni èmi yóò fọ́ sí wẹ́wẹ́, àwọn ọ̀pá ìdábùú tí a fi irin ṣe ni èmi yóò sì ké lulẹ̀. Dájúdájú, èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ìṣúra tí ó wà nínú òkùnkùn àti àwọn ìṣúra fífarasin ní àwọn ibi ìlùmọ́.’”—Aísáyà 45:1-3a.

      4. (a) Kí ni ìdí tí Jèhófà fi pe Kírúsì ní “ẹni àmì òróró” òun? (b) Báwo ni Jèhófà yóò ṣe rí sí i pé Kírúsì ṣẹ́gun?

      4 Jèhófà gbẹnu Aísáyà bá Kírúsì sọ̀rọ̀ bíi pé Kírúsì ti wà láyé, bẹ́ẹ̀ wọn ò sì tíì bí i láyé ìgbà Aísáyà. (Róòmù 4:17) Nítorí yíyàn tí Jèhófà ti yan Kírúsì ṣáájú láti ṣe iṣẹ́ pàtó kan, a lè sọ pé Kírúsì jẹ́ “ẹni àmì òróró” Ọlọ́run. Bó sì ti jẹ́ pé Ọlọ́run ń ṣáájú rẹ̀ lọ, yóò borí àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì sọ àwọn ọba di aláìlágbára tí wọn ò fi ní lè mí fín níwájú rẹ̀. Nígbà tí Kírúsì bá sì wá láti kọ lu Bábílónì, Jèhófà yóò rí sí i pé ilẹ̀kùn ìlú ńlá náà wà ní ṣíṣí sílẹ̀, wọn kò ní wúlò àní bíi ti ẹnubodè tí wọ́n fọ́ sí wẹ́wẹ́. Jèhófà yóò máa ṣáájú Kírúsì lọ, tí yóò sì máa mú kí gbogbo ohun ìdìgbòlù pa rẹ́ mọ́lẹ̀. Àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀, agbo ọmọ ogun Kírúsì yóò ṣẹ́gun ìlú ńlá náà, wọn yóò sì sọ “àwọn ìṣúra fífarasin,” ìyẹn àwọn ọrọ̀ Bábílónì tí wọ́n kó pa mọ́ sínú àwọn àjà tó ṣókùnkùn biribiri di tiwọn. Ohun tí Aísáyà sọ tẹ́lẹ̀ nìyẹn. Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ?

      5, 6. Ìgbà wo ni àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìṣubú Bábílónì ṣẹ, báwo ló sì ṣe ṣẹ?

      5 Lọ́dún 539 ṣááju Sànmánì Tiwa, ìyẹn nǹkan bí igba ọdún lẹ́yìn tí Aísáyà kọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí, Kírúsì wá sí ibi odi Bábílónì lóòótọ́ láti wá kọlu ìlú náà. (Jeremáyà 51:11, 12) Ṣùgbọ́n, àwọn ará Bábílónì ò tilẹ̀ fi í pè. Wọ́n gbà pé mìmì kan ò lè mi ìlú àwọn. Àwòṣífìlà ni odi ìlú wọn kúkú jẹ́ lókè àwọn yàrà jíjìn tí omi Odò Yúfírétì kún dẹ́múdẹ́mú, ara ètò ààbò ìlú sì ni omi yìí jẹ́. Láti ohun tó lé ní ọgọ́rùn-ún ọdún sẹ́yìn, ọ̀tá kankan ò sáà tíì bá Bábílónì lábo rí! Àní ọkàn Bẹliṣásárì ọba Bábílónì tó ń gbé ìlú náà tilẹ̀ balẹ̀ débi pé àsè lòun àtàwọn èèyàn ààfin rẹ̀ ń jẹ lọ ràì. (Dáníẹ́lì 5:1) Lóru yẹn, ìyẹn òru October 5 mọ́jú October 6, ni Kírúsì parí bírà kan tó ń fi ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ ológun dá.

      6 Àwọn onímọ̀ iṣẹ́ ẹ̀rọ Kírúsì lọ ya omi Odò Yúfírétì ní apá òkè níbi tí omi ti ń ṣàn wá sí Bábílónì, wọ́n wá darí omi yẹn gba ọ̀nà ibòmíràn lọ, ni omi ò bá ṣàn wá síhà gúúsù níbi tí ìlú wà mọ́. Láìpẹ́ láìjìnnà, omi odò tó wà nínú Bábílónì àti ní àyíká rẹ̀ wá fà débi pé àwọn agbo ọmọ ogun Kírúsì lè wọ́dò kọjá lọ sí àárín gbùngbùn ìlú gan-an. (Aísáyà 44:27; Jeremáyà 50:38) Ó sì jẹ́ ìyàlẹ́nu pé, gẹ́lẹ́ bí Aísáyà ṣe sọ tẹ́lẹ̀, ṣíṣí ni àwọn ibodè ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ odò yẹn wà. Ni agbo ọmọ ogun Kírúsì bá rọ́ wọnú Bábílónì, wọ́n gba ààfin, wọ́n sì pa Bẹliṣásárì Ọba. (Dáníẹ́lì 5:30) Òru ọjọ́ kan ṣoṣo ni wọ́n ṣẹ́gun rẹ̀ pátápátá. Bí Bábílónì ṣe ṣubú nìyẹn o, tí àsọtẹ́lẹ̀ yìí sì ṣẹ láìsí ohunkóhun tó yingin.

  • Jèhófà—“Ọlọ́run Òdodo àti Olùgbàlà”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • Ìdí Tí Jèhófà Yóò Fi Ṣojú Rere sí Kírúsì

      8. Kí ni ìdí kan tí Jèhófà fi jẹ́ kí Kírúsì ṣẹ́gun Bábílónì?

      8 Lẹ́yìn tí Jèhófà ti sọ ẹni tí yóò ṣẹ́gun Bábílónì àti ọ̀nà tó máa gbà ṣe é, ó wá ṣàlàyé ìdí kan tí òun fi máa jẹ́ kí Kírúsì ṣẹ́gun. Jèhófà fi àsọtẹ́lẹ̀ bá Kírúsì sọ̀rọ̀ pé ìdí tí òun fi ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé “kí o lè mọ̀ pé èmi ni Jèhófà, Ẹni tí ó fi orúkọ rẹ pè ọ́, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.” (Aísáyà 45:3b) Ó tọ́ gan-an pé kí alákòóso agbára ayé kẹrin nínú ìtàn Bíbélì yìí mọ̀ pé ìtìlẹyìn Jèhófà, Ọba Aláṣẹ Àgbáyé, ẹni tó ga ju òun lọ, ló mú kí ìṣẹ́gun òun tó ga jù lọ yìí ṣeé ṣe. Dandan ni kí Kírúsì gbà pé Jèhófà, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, lẹni tó pe òun tàbí tó gbéṣẹ́ lé òun lọ́wọ́. Àkọsílẹ̀ Bíbélì sì fi hàn pé Kírúsì gbà bẹ́ẹ̀ lóòótọ́ pé látọwọ́ Jèhófà ni ìṣẹ́gun ńláǹlà òun ti wá.—Ẹ́sírà 1:2, 3.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́