-
“Àkókò Ìtẹ́wọ́gbà”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
28. (a) Ọ̀rọ̀ wo ni Jèhófà sọ láti mú un dá àwọn èèyàn rẹ̀ lójú lẹ́ẹ̀kan sí i pé òun yóò dá wọn nídè? (b) Kí ni ẹ̀jẹ́ tí Jèhófà ṣì máa san fún àwọn èèyàn rẹ̀?
28 Àwọn kan lára àwọn tó wà nígbèkùn ní Bábílónì lè bẹ̀rẹ̀ sí rò ó pé, ‘Ṣé Ísírẹ́lì wá lè bọ́ lóko òǹdè báyìí?’ Jèhófà ro ti ìbéèrè yìí pẹ̀lú, ìyẹn ló fi béèrè pé: “A ha lè kó àwọn tí alágbára ńlá ti kó tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀ bí, tàbí kẹ̀, ẹgbẹ́ àwọn òǹdè ti afìkà-gboni-mọ́lẹ̀ ha lè sá àsálà bí?” (Aísáyà 49:24) Bẹ́ẹ̀ ni o. Jèhófà mú un dá wọn lójú pé: “Àní ẹgbẹ́ àwọn òǹdè ti alágbára ńlá ni a óò kó lọ, àwọn tí a sì ti kó tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀ nípasẹ̀ afìkà-gboni-mọ́lẹ̀ pàápàá yóò sá àsálà.” (Aísáyà 49:25a) Ìtùnú gbáà ni ìdánilójú tí Jèhófà fún wọn yìí jẹ́ o! Àní sẹ́, Jèhófà tún jẹ́ ẹ̀jẹ́ pé òun yóò dáàbò bo àwọn èèyàn òun láfikún sí títẹ́wọ́ gbà wọ́n. Ó sọ ọ́ ní ṣàkó pé: “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ń bá ọ fà á, èmi tìkára mi yóò bá a fà á, àwọn ọmọ rẹ ni èmi fúnra mi yóò sì gbà là.” (Aísáyà 49:25b) Ẹ̀jẹ́ yẹn kò yí padà. Gẹ́gẹ́ bí Sekaráyà 2:8 ṣe sọ, Jèhófà sọ fún àwọn èèyàn rẹ̀ pé: “Ẹni tí ó bá fọwọ́ kàn yín ń fọwọ́ kan ẹyinjú mi.” Ní tòótọ́, àkókò ìtẹ́wọ́gbà yẹn la wà báyìí o, àkókò tí àǹfààní ṣí sílẹ̀ fún àwọn èèyàn jákèjádò ayé láti dà wìtìwìtì lọ sí Síónì nípa tẹ̀mí. Ṣùgbọ́n àkókò ìtẹ́wọ́gbà yẹn máa dópin o.
-
-
“Àkókò Ìtẹ́wọ́gbà”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
30. Àwọn iṣẹ́ ìgbàlà wo ni Jèhófà ṣe nítorí àwọn èèyàn rẹ̀, kí ló sì máa tó ṣe láìpẹ́?
30 Ìgbà tí Jèhófà lo Kírúsì láti fi dá àwọn èèyàn Rẹ̀ nídè kúrò nígbèkùn Bábílónì lọ̀rọ̀ wọ̀nyí kọ́kọ́ ṣẹ. Wọ́n tún ṣẹ pẹ̀lú lọ́dún 1919 nígbà tí Jèhófà lo Jésù Kristi Ọmọ rẹ̀ tó gorí ìtẹ́ láti fi dá àwọn èèyàn Rẹ̀ nídè kúrò lóko ẹrú nípa tẹ̀mí. Ìyẹn ni Bíbélì fi pe Jèhófà àti Jésù ní olùgbàlà. (Títù 2:11-13; 3:4-6) Jèhófà ni Olùgbàlà wa, Jésù tó jẹ́ Mèsáyà sì jẹ́ “Olórí Aṣojú” rẹ̀. (Ìṣe 5:31) Ní tòdodo, àgbàyanu làwọn iṣẹ́ ìgbàlà tí Ọlọ́run tipasẹ̀ Jésù Kristi ṣe. Jèhófà ń lo ìhìn rere láti fi dá àwọn ọlọ́kàn títọ́ nídè kúrò nínú ìgbèkùn ìsìn èké. Ó ń lo ẹbọ ìràpadà láti fi gbà wọ́n kúrò nígbèkùn ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú. Lọ́dún 1919, ó gba àwọn arákùnrin Jésù kúrò nígbèkùn nípa tẹ̀mí. Nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì tó sì ń bọ̀ kánkán yìí, yóò gba ogunlọ́gọ̀ ńlá àwọn olóòótọ́ èèyàn là kúrò lọ́wọ́ ìparun tí yóò wá sórí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
-