ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Ẹ Má Ṣe Gbẹ́kẹ̀ Yín Lé Àwọn Ọ̀tọ̀kùlú”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 13. Kí ní ń bẹ níwájú fún Jésù, síbẹ̀ báwo ló ṣe fi ìgboyà hàn?

      13 Àwọn kan lára àwọn tí kò tẹ́wọ́ gba Ọmọ bíbí kan ṣoṣo ti Jèhófà yìí ṣe inúnibíni sí i, àsọtẹ́lẹ̀ sì ti sọ bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀, pé: “Ẹ̀yìn mi ni mo fi fún àwọn akọluni, mo sì fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irun tu. Ojú mi ni èmi kò fi pa mọ́ fún àwọn ohun tí ń tẹ́ni lógo àti itọ́.” (Aísáyà 50:6) Gẹ́gẹ́ bí àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣe wí, Mèsáyà yóò jìyà lọ́wọ́ àwọn alátakò rẹ̀, wọ́n á sì tẹ́ ẹ. Jésù sì mọ̀ bẹ́ẹ̀. Ó sì mọ bí inúnibíni yìí ṣe máa tó. Síbẹ̀, bí àsìkò tí ó máa lò láyé ṣe ń tán lọ, ẹ̀rù kò bà á rárá. Ó fi ìgboyà tó lágbára bí akọ òkúta gbéra lọ sí Jerúsálẹ́mù, níbi tí wọn yóò ti gbẹ̀mí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn. Bí wọ́n ṣe ń lọ lọ́nà ibẹ̀, Jésù sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Àwa nìyí, tí a ń tẹ̀ síwájú gòkè lọ sí Jerúsálẹ́mù, a ó sì fa Ọmọ ènìyàn lé àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé òfin lọ́wọ́, wọn yóò sì dá a lẹ́bi ikú, wọn yóò sì fà á lé àwọn ènìyàn àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, wọn yóò sì fi í ṣe yẹ̀yẹ́, wọn yóò sì tutọ́ sí i lára, wọn yóò sì nà án lọ́rẹ́, wọn yóò sì pa á, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ mẹ́ta lẹ́yìn náà, yóò dìde.” (Máàkù 10:33, 34) Àwọn èèyàn tó sì yẹ kí òye yé jù bẹ́ẹ̀ lọ, ìyẹn àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé, ni wọ́n máa wà nídìí ṣíṣe tí wọ́n yóò ṣe é ṣúkaṣùka yìí.

      14, 15. Báwo ni ọ̀rọ̀ Aísáyà pé wọn yóò lu Jésù pé wọn yóò sì tẹ́ ẹ ṣe ṣẹ?

      14 Ní òru Nísàn 14, ọdún 33 Sànmánì Tiwa, Jésù àti àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ mélòó kan wà nínú ọgbà Gẹtisémánì. Ó ń gbàdúrà. Lójijì, àwọn èèyànkéèyàn kan ya lù wọ́n, wọ́n sì mú un. Ṣùgbọ́n kò bẹ̀rù rárá. Ó mọ̀ pé Jèhófà ń bẹ lẹ́yìn òun. Jésù jẹ́ kó dá àwọn àpọ́sítélì rẹ̀ tí jìnnìjìnnì mú lójú pé ká ní pé òun fẹ́ ni, òun ì bá ké pe Baba òun pé kí ó rán àwọn áńgẹ́lì tó ju líjíónì méjìlá wá láti wá gba òun sílẹ̀, ó wá ní: “Bí ọ̀ràn bá rí bẹ́ẹ̀, báwo ni a ó ṣe mú Ìwé Mímọ́ ṣẹ pé ó gbọ́dọ̀ ṣẹlẹ̀ lọ́nà yìí?”—Mátíù 26:36, 47, 53, 54.

      15 Gbogbo ohun tí àsọtẹ́lẹ̀ sọ nípa àdánwò àti ikú Mèsáyà ló ṣẹ pátá. Lẹ́yìn ìgbẹ́jọ́ èrú kan tí àjọ Sànhẹ́dírìn ṣe, Pọ́ńtíù Pílátù ṣàyẹ̀wò ẹjọ́ Jésù, ó sì ní kí wọ́n lu Jésù. Àwọn ọmọ ogun Róòmù tún ‘fi ọ̀pá esùsú gbá a ní orí, wọ́n sì tutọ́ sí i lára.’ Bí ọ̀rọ̀ Aísáyà ṣe ṣẹ nìyẹn. (Máàkù 14:65; 15:19; Mátíù 26:67, 68) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Bíbélì kò mẹ́nu kàn án pé wọ́n fà lára irùngbọ̀n Jésù tu, tó jẹ́ àmì pé wọ́n kórìíra rẹ̀ dé góńgó, ó dájú pé èyí ṣẹlẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Aísáyà ti sọ ọ́ tẹ́lẹ̀.c—Nehemáyà 13:25.

  • “Ẹ Má Ṣe Gbẹ́kẹ̀ Yín Lé Àwọn Ọ̀tọ̀kùlú”
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • c Ẹ sì wá wò o, Aísáyà 50:6 nínú ìtumọ̀ ti Septuagint kà pé: “Mo fi ẹ̀yìn mi gba bílálà oníkókó, mo sì fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ gba ẹ̀ṣẹ́.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́