ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ọ̀rọ̀ Àgàn Náà Dayọ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 9, 10. Kí ni ìtọ́ni tí obìnrin kan tó ń gbé inú àgọ́ láyé àtijọ́ gbà pé kí ó ‘mú kí ibi àgọ́ rẹ̀ túbọ̀ ní àyè gbígbòòrò’ yóò túmọ̀ sí fún un, kí sì nìdí tí yóò fi jẹ́ àkókò ìdùnnú fún obìnrin yẹn?

      9 Aísáyà wá gbẹ́nu lé àsọtẹ́lẹ̀ nípa àkókò tí ìbísí kíkàmàmà yóò dé, ó ní: “Mú kí ibi àgọ́ rẹ túbọ̀ ní àyè gbígbòòrò. Kí wọ́n sì na àwọn aṣọ àgọ́ ibùgbé rẹ títóbilọ́lá. Má fawọ́ sẹ́yìn. Mú kí àwọn okùn àgọ́ rẹ gùn sí i, kí o sì mú àwọn ìkànlẹ̀ àgọ́ tìrẹ wọ̀nyẹn le. Nítorí pé ìwọ yóò ya sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn ọmọ tìrẹ yóò sì gba àwọn orílẹ̀-èdè pàápàá, wọn yóò sì máa gbé àwọn ìlú ńlá tí ó ti di ahoro pàápàá. Má fòyà, nítorí pé a kì yóò kó ìtìjú bá ọ; má sì jẹ́ kí ìtẹ́lógo bá ọ, nítorí pé a kì yóò já ọ kulẹ̀. Nítorí pé ìwọ yóò gbàgbé ìtìjú ìgbà èwe rẹ pàápàá, ẹ̀gàn ìgbà opó rẹ tí ń bá a nìṣó ni ìwọ kì yóò sì rántí mọ́.”—Aísáyà 54:2-4.

  • Ọ̀rọ̀ Àgàn Náà Dayọ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
    • 11. (a) Báwo ni ìbùkún ṣe dé bá “obìnrin” Ọlọ́run ní ọ̀run lọ́dún 1914? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.) (b) Láti ọdún 1919 síwájú, irú ìbùkún wo ló ti bá àwọn ẹni àmì òróró lórí ilẹ̀ ayé?

      11 Irú ìgbà àmúdọ̀tun bẹ́ẹ̀ la wá fi jíǹkí Jerúsálẹ́mù orí ilẹ̀ ayé lẹ́yìn tí ìgbèkùn wọn ní Bábílónì dópin. “Jerúsálẹ́mù ti òkè” sì tilẹ̀ tún gba ìbùkún tó ju ìyẹn lọ.a Láti ọdún 1919 ní pàtàkì ni “àwọn ọmọ” rẹ̀ ẹni àmì òróró ti ń gbilẹ̀ nínú ipò ìmúbọ̀sípò nípa tẹ̀mí tí wọ́n wà. (Aísáyà 61:4; 66:8) Wọ́n “gba àwọn orílẹ̀-èdè” ní ti pé wọ́n tàn ká lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀ láti wá àwọn tó máa dara pọ̀ mọ́ ìdílé wọn nípa tẹ̀mí. Ìyẹn ló fi di pé àwọn ọmọ tó jẹ́ ẹni àmì òróró yìí wá bẹ̀rẹ̀ sí rọ́ wọlé wìtìwìtì. Ó jọ pé láàárín ọdún 1930 sí 1939 ni ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ iye wọn, tó jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó lé ẹgbàajì, ti pé. (Ìṣípayá 14:3) Ní àsìkò tí à ń wí yìí, wọn kò fi kíkó àwọn ẹni àmì òróró jọ ṣe ìdí pàtàkì tí wọ́n fi ń wàásù mọ́. Síbẹ̀, ìbísí yìí kò mọ sórí àwọn ẹni àmì òróró nìkan.

      12. Láfikún sí àwọn ẹni àmì òróró, àwọn wo la tún ti ń kó jọ sínú ìjọ Kristẹni láti ọdún 1930 wá?

      12 Jésù fúnra rẹ̀ sọ tẹ́lẹ̀ pé, yàtọ̀ sí “agbo kékeré” ti àwọn ẹni àmì òróró tó jẹ́ arákùnrin òun, òun yóò tún ní “àwọn àgùntàn mìíràn” tí a óò ní láti mú wọlé wá sínú agbo àgùntàn ti àwọn Kristẹni tòótọ́. (Lúùkù 12:32; Jòhánù 10:16) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn olóòótọ́ wọ̀nyí, tó jẹ́ alábàákẹ́gbẹ́ àwọn ẹni àmì òróró yìí, kì í ṣe ara àwọn ẹni àmì òróró tí í ṣe ọmọ “Jerúsálẹ́mù ti òkè,” wọ́n ń kó ipa pàtàkì kan tí àsọtẹ́lẹ̀ ti sọ tipẹ́tipẹ́. (Sekaráyà 8:23) Ìkójọpọ̀ wọn láti ọdún 1930 títí dòní, ti mú kí “ogunlọ́gọ̀ ńlá” wọn wọlé wá, tó fi jẹ́ pé kò sígbà tí ìjọ Kristẹni tíì gbilẹ̀ tó báyìí rí. (Ìṣípayá 7:9, 10) Lónìí, ogunlọ́gọ̀ ńlá yẹn ti wá di àràádọ́ta ọ̀kẹ́. Gbogbo ìbísí yìí wá ń béèrè pé kí á bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ àwọn Gbọ̀ngàn Ìjọba, Gbọ̀ngàn Àpéjọ, àti àwọn ẹ̀ka iléeṣẹ́ púpọ̀ sí i ní kánjúkánjú. Ẹ ò rí i pé ọ̀rọ̀ Aísáyà túbọ̀ wá bá a mu gan-an ni lásìkò yìí. Àǹfààní ńlá mà ló jẹ́ fún wa láti kópa nínú ìmúgbòòrò tí a sọ tẹ́lẹ̀ yìí o!

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́