-
Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ JíÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
18. Báwo la ṣe ṣàpèjúwe gíga tí Jèhófà ga fíofío, síbẹ̀ ọ̀nà onífẹ̀ẹ́ wo ló gbà ń ṣàníyàn nípa ẹni?
18 Ìgbà yìí ni wòlíì Aísáyà wá sọ ọ̀rọ̀ tí a fà yọ ní ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ yẹn, tó sọ pé: “Èyí ni ohun tí Ẹni Gíga àti Ẹni Gíga Fíofío, tí ń gbé títí láé àti ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ mímọ́, wí: ‘Ibi gíga àti ibi mímọ́ ni ibi tí mo ń gbé, àti pẹ̀lú ẹni tí a tẹ̀ rẹ́, tí ó sì rẹ̀wẹ̀sì ní ẹ̀mí, láti mú ẹ̀mí àwọn ẹni rírẹlẹ̀ sọ jí àti láti mú ọkàn-àyà àwọn tí a tẹ̀ rẹ́ sọ jí.’” (Aísáyà 57:15) Ibi tó ga jù lọ ní ọ̀run ni ìtẹ́ Jèhófà wà. Kò tún sí ibòmíràn tó ròkè tàbí tó ga ju ibẹ̀ lọ. Ó mà tuni nínú gan-an o láti mọ̀ pé, láti ibẹ̀, ó ń rí gbogbo ohun tó ń lọ, àti pé yàtọ̀ sí pé ó ń rí ẹ̀ṣẹ̀ tí àwọn ẹni burúkú ń dá, ó tún ń rí iṣẹ́ òdodo tí àwọn tó ń ṣakitiyan láti sìn ín ń ṣe! (Sáàmù 102:19; 103:6) Ẹ̀wẹ̀, ó ń gbọ́ bí àwọn tí wọ́n ń ni lára ṣe ń kérora, ó sì ń mú ọkàn àyà àwọn ẹni tí a tẹ̀ rẹ́ sọjí. Ọ̀rọ̀ yìí ti ní láti wọ àwọn tó ronú pìwà dà lára àwọn Júù ayé àtijọ́ lọ́kàn gan-an ni. Ó dájú pé ó wọ àwa náà lọ́kàn lóde òní pẹ̀lú.
-
-
Jèhófà Mú Ẹ̀mí Àwọn Ẹni Rírẹlẹ̀ Sọ JíÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
-
-
21. (a) Báwo ni Jèhófà ṣe mú ẹ̀mí àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró sọjí lọ́dún 1919? (b) Ànímọ́ wo ló yẹ kí àwa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan fi kọ́ra?
21 Lọ́dún 1919, Jèhófà “Ẹni Gíga àti Ẹni Gíga Fíofío” fi hàn pé òun bìkítà nípa ire àwọn ẹni àmì òróró pẹ̀lú. Nítorí ẹ̀mí ìròbìnújẹ́ àti ìrẹ̀lẹ̀ tí wọ́n ní, Jèhófà, Ọlọ́run gíga jù lọ fi inú rere kíyè sí ìpọ́njú wọn, ó sì gbà wọ́n kúrò nígbèkùn Bábílónì. Ó mú gbogbo ohun ìdìgbòlù kúrò lọ́nà, ó ṣamọ̀nà wọn tí wọ́n fi gba òmìnira kí wọ́n lè máa ṣe ìjọsìn mímọ́ sí i. Bí ọ̀rọ̀ tí Jèhófà gbẹnu Aísáyà sọ ṣe ṣẹ nígbà yẹn nìyẹn. Àwọn ìlànà tí yóò wà títí ayérayé, tí ó kan olúkúlùkù wa sì ń bẹ nínú ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn. Ìjọsìn àwọn tí ó bá ní ọkàn ìrẹ̀lẹ̀ nìkan ni Jèhófà máa ń tẹ́wọ́ gbà. Bí èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run bá sì dẹ́ṣẹ̀, kí onítọ̀hún tètè mọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ní ẹ̀ṣẹ̀, kí ó gba ìbáwí, kí ó sì tún àwọn ọ̀nà rẹ̀ ṣe. Ǹjẹ́ kí á má ṣe gbàgbé láé pé Jèhófà a máa mú àwọn onírẹ̀lẹ̀ lára dá, a sì máa tù wọ́n nínú, àmọ́ a máa “kọ ojú ìjà sí àwọn onírera.”—Jákọ́bù 4:6.
-