-
“Ẹ Jẹ́ Kí A Mú Àwọn Ọ̀ràn Tọ́”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
9, 10. Báwo ni ìmọ́tótó ti ṣe pàtàkì tó nínú ìjọsìn wa sí Jèhófà?
9 Jèhófà, Ọlọ́run ìyọ́nú, wá bẹ̀rẹ̀ sí lo ohùn pẹ̀lẹ́ tó túbọ̀ fani mọ́ra wàyí. Ó ní: “Ẹ wẹ̀; ẹ jẹ́ kí ara yín mọ́; ẹ mú búburú ìbánilò yín kúrò ní iwájú mi; ẹ ṣíwọ́ ṣíṣe búburú. Ẹ kọ́ ṣíṣe rere; ẹ wá ìdájọ́ òdodo; ẹ tún ojú ìwòye aninilára ṣe; ẹ ṣe ìdájọ́ ọmọdékùnrin aláìníbaba; ẹ gba ẹjọ́ opó rò.” (Aísáyà 1:16, 17) Oríṣi ohun àìgbọ́dọ̀máṣe, tàbí àṣẹ mẹ́sàn-án la rí níhìn-ín. Mẹ́rin àkọ́kọ́ jẹ́ ti ṣíṣe àtúnṣe nítorí wọ́n jẹ mọ́ yíyọwọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ dídá; márùn-ún tó kù jẹ mọ́ rere ṣíṣe, tó lè múni rí ìbùkún gbà lọ́dọ̀ Jèhófà.
10 Apá pàtàkì nínú ìjọsìn mímọ́ gaara ní ìwẹ̀ àti ìmọ́tótó jẹ́ nígbà gbogbo. (Ẹ́kísódù 19:10, 11; 30:20; 2 Kọ́ríńtì 7:1) Àmọ́, ohun tí Jèhófà ń fẹ́ ni pé kí ìwẹ̀nùmọ́ yẹn dénú lọ́hùn-ún, àní kó wọnú ọkàn àwọn olùjọsìn rẹ̀ lọ. Mímọ́ tónítóní nípa tẹ̀mí àti nínú ìwà ló ṣe pàtàkì jù lọ, ìyẹn sì ni ohun tí Jèhófà ń tọ́ka sí. Àṣẹ méjì àkọ́kọ́ ní Ais 1 ẹsẹ kẹrìndínlógún kì í ṣe àsọtúnsọ lásán. Ẹnì kan tó jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ìlò èdè Hébérù dá a lábàá pé, “ẹ wẹ̀,” tó ṣáájú tọ́ka sí ìgbésẹ̀ àkọ́kọ́ nínú ìmọ́tótó, nígbà tí ìkejì, “ẹ jẹ́ kí ara yín mọ́,” tọ́ka sí ìsapá tí a ń ṣe nìṣó kí ìmọ́tótó yẹn lè máa bá a lọ bẹ́ẹ̀.
11. Láti lè gbéjà ko ẹ̀ṣẹ̀, kí ló yẹ kí a ṣe, kí ni a kò sì gbọ́dọ̀ ṣe láé?
11 Kò sóhun tí a lè fi pa mọ́ fún Jèhófà. (Jóòbù 34:22; Òwe 15:3; Hébérù 4:13) Nítorí náà, ohun kan ni àṣẹ rẹ̀ tó sọ pé, “Ẹ mú búburú ìbánilò yín kúrò ní iwájú mi,” lè túmọ̀ sí, ìyẹn ni, láti ṣíwọ́ ibi ṣíṣe. Ìyẹn túmọ̀ sí pé ká má gbìyànjú láti bo ẹ̀ṣẹ̀ ńlá mọ́lẹ̀, nítorí pé bí a bá ṣe bẹ́ẹ̀ ńṣe là ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀. Òwe 28:13 kìlọ̀ pé: “Ẹni tí ó bá ń bo àwọn ìrélànàkọjá rẹ̀ mọ́lẹ̀ kì yóò kẹ́sẹ járí, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jẹ́wọ́ tí ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ni a ó fi àánú hàn sí.”
-
-
“Ẹ Jẹ́ Kí A Mú Àwọn Ọ̀ràn Tọ́”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
14. Ìhìn iṣẹ́ dáadáa wo ni Aísáyà 1:16, 17 gbé jáde?
14 Ìsọfúnni tí Jèhófà fi àwọn àṣẹ mẹ́sàn-án wọ̀nyí gbé jáde mà fẹsẹ̀ rinlẹ̀ o, ó mà dára o! Nígbà mìíràn àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ máa ń ro ara wọn pin pé àwọn ò kàn tiẹ̀ lè ṣe rere mọ́ ni. Irú àwọn èrò bẹ́ẹ̀ a máa múni rẹ̀wẹ̀sì. Pẹ̀lúpẹ̀lù, wọ́n tún lòdì. Jèhófà mọ̀—ó sì ń fẹ́ ká mọ̀—pé pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Òun, ẹlẹ́ṣẹ̀ èyíkéyìí lè ṣíwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ dídá, kó sì yí padà, kó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe rere dípò ẹ̀ṣẹ̀ tó ń dá.
-