-
“Ẹ Jẹ́ Kí A Mú Àwọn Ọ̀ràn Tọ́”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
9, 10. Báwo ni ìmọ́tótó ti ṣe pàtàkì tó nínú ìjọsìn wa sí Jèhófà?
9 Jèhófà, Ọlọ́run ìyọ́nú, wá bẹ̀rẹ̀ sí lo ohùn pẹ̀lẹ́ tó túbọ̀ fani mọ́ra wàyí. Ó ní: “Ẹ wẹ̀; ẹ jẹ́ kí ara yín mọ́; ẹ mú búburú ìbánilò yín kúrò ní iwájú mi; ẹ ṣíwọ́ ṣíṣe búburú. Ẹ kọ́ ṣíṣe rere; ẹ wá ìdájọ́ òdodo; ẹ tún ojú ìwòye aninilára ṣe; ẹ ṣe ìdájọ́ ọmọdékùnrin aláìníbaba; ẹ gba ẹjọ́ opó rò.” (Aísáyà 1:16, 17) Oríṣi ohun àìgbọ́dọ̀máṣe, tàbí àṣẹ mẹ́sàn-án la rí níhìn-ín. Mẹ́rin àkọ́kọ́ jẹ́ ti ṣíṣe àtúnṣe nítorí wọ́n jẹ mọ́ yíyọwọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ dídá; márùn-ún tó kù jẹ mọ́ rere ṣíṣe, tó lè múni rí ìbùkún gbà lọ́dọ̀ Jèhófà.
-
-
“Ẹ Jẹ́ Kí A Mú Àwọn Ọ̀ràn Tọ́”Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
12. (a) Èé ṣe tó fi ṣe pàtàkì pé kí a “kọ́ ṣíṣe rere”? (b) Báwo ni àwọn alàgbà ní pàtàkì ṣe lè fi ìtọ́ni tó sọ pé “ẹ wá ìdájọ́ òdodo,” àti “ẹ tún ojú ìwòye aninilára ṣe” sílò?
12 Ẹ̀kọ́ púpọ̀ ni a lè rí kọ́ látinú àwọn ohun dáadáa tí Jèhófà pa láṣẹ fúnni láti ṣe ní Aísáyà orí kìíní, ẹsẹ kẹtàdínlógún. Ṣàkíyèsí pé kò kàn sọ pé “ẹ ṣe rere” ṣùgbọ́n ó ní “ẹ kọ́ ṣíṣe rere.” Fífúnra ẹni kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ló lè múni lóye ohun tó dára lójú Ọlọ́run kó sì wuni láti ṣe. Bákan náà, Jèhófà kò kàn sọ pé “ẹ ṣe ìdájọ́ òdodo” ṣùgbọ́n ó ní “ẹ wá ìdájọ́ òdodo.” Àní àwọn alàgbà onírìírí pàápàá ní láti wá inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fínnífínní láti lè mọ ọ̀nà tó jẹ́ ti ìdájọ́ òdodo nígbà tí àwọn ọ̀ràn kan bá díjú. Ó sì tún jẹ́ ojúṣe wọn láti “tún ojú ìwòye aninilára ṣe,” gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Jèhófà tó tẹ̀ lé e ṣe wí. Ìtọ́ni wọ̀nyí ṣe pàtàkì fún àwọn Kristẹni olùṣọ́ àgùntàn lónìí, nítorí pé wọ́n ń fẹ́ láti dáàbò bo agbo kúrò lọ́wọ́ “àwọn aninilára ìkookò.”—Ìṣe 20:28-30.
13. Báwo ni àwa lónìí ṣe lè fi àṣẹ tó kan ọ̀ràn ọmọdékùnrin aláìníbaba àti opó sílò?
13 Àṣẹ méjì tó gbẹ̀yìn jẹ mọ́ ọ̀ràn àwọn tí ìyà lè tètè jẹ nínú àwọn ènìyàn Ọlọ́run—àwọn aláìníbaba àti opó. Irú wọn làwọn èèyàn ayé yìí máa ń tètè rẹ́ jẹ; èyí kò gbọ́dọ̀ wáyé láàárín àwọn ènìyàn Ọlọ́run. Àwọn alàgbà onífẹ̀ẹ́ a máa “ṣe ìdájọ́” nítorí àwọn ọmọdékùnrin àti ọmọdébìnrin aláìníbaba tó wà nínú ìjọ, wọn a ṣèrànwọ́ láti rí i pé wọ́n rí ìdájọ́ òdodo gbà, pé wọ́n sì wà láàbò nínú ayé tó ń fẹ́ máa rẹ́ wọn jẹ tó sì ń fẹ́ máa kó ìwà ìbàjẹ́ ràn wọ́n. Àwọn alàgbà a máa “gba ẹjọ́” opó “rò” tàbí pé wọ́n a máa “gbèjà” àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Hébérù náà ṣe tún lè túmọ̀ sí. Ní tòdodo, gbogbo Kristẹni ní láti jẹ́ ibi ìsádi, ìtùnú, àti ìdájọ́ òdodo fún àwọn aláìní àárín wa nítorí pé wọ́n ṣeyebíye lójú Jèhófà.—Míkà 6:8; Jákọ́bù 1:27.
14. Ìhìn iṣẹ́ dáadáa wo ni Aísáyà 1:16, 17 gbé jáde?
14 Ìsọfúnni tí Jèhófà fi àwọn àṣẹ mẹ́sàn-án wọ̀nyí gbé jáde mà fẹsẹ̀ rinlẹ̀ o, ó mà dára o! Nígbà mìíràn àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ máa ń ro ara wọn pin pé àwọn ò kàn tiẹ̀ lè ṣe rere mọ́ ni. Irú àwọn èrò bẹ́ẹ̀ a máa múni rẹ̀wẹ̀sì. Pẹ̀lúpẹ̀lù, wọ́n tún lòdì. Jèhófà mọ̀—ó sì ń fẹ́ ká mọ̀—pé pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Òun, ẹlẹ́ṣẹ̀ èyíkéyìí lè ṣíwọ́ ẹ̀ṣẹ̀ dídá, kó sì yí padà, kó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe rere dípò ẹ̀ṣẹ̀ tó ń dá.
-