ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Bàbá Kan Àtàwọn Ọlọ̀tẹ̀ Ọmọ Rẹ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • Ẹranko Lásánlàsàn Mọ̀ Jù Wọ́n Lọ

      5. Ní ìyàtọ̀ sí ìwà Ísírẹ́lì, ọ̀nà wo ni akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ fi lẹ́mìí àrótì?

      5 Nípasẹ̀ Aísáyà, Jèhófà sọ pé: “Akọ màlúù mọ ẹni tí ó ra òun dunjú, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ ẹran olúwa rẹ̀; Ísírẹ́lì alára kò mọ̀, àwọn ènìyàn mi kò hùwà lọ́nà òye.” (Aísáyà 1:3)a Akọ màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ jẹ́ ẹranko arẹrù tí àwọn tí ń gbé Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ayé mọ̀ dáadáa. Ní tòótọ́, àwọn ènìyàn Júdà wọ̀nyẹn kò ní jiyàn rárá pé àwọn ẹranko lásánlàsàn wọ̀nyẹn pàápàá lẹ́mìí àrótì, wọ́n mọ̀ dájú pé àwọn lólúwa. Láti kín ọ̀rọ̀ yìí lẹ́yìn, fetí sí ìṣẹ̀lẹ̀ kan tó ṣojú ọ̀gbẹ́ni kan tí ń ṣèwádìí lórí Bíbélì, ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún ṣẹlẹ̀ nírọ̀lẹ́ ọjọ́ kan ní ìlú kan ní Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ayé: “Gbàrà tí agbo ẹran náà wọnú ìlú ni wọ́n tú ká. Akọ màlúù kọ̀ọ̀kan mọ olúwa rẹ̀ dunjú, àti ọ̀nà ilé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ tó gba inú kọ̀rọ̀ já sí gbangba látinú horo já sí horo kò dàrú mọ́ ọn lójú rárá ni. Ní ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ẹnu ọ̀nà ilé ló gbà lọ tààrà, ó sì wọnú ‘ibùjẹran ti ọ̀gá rẹ̀.’”

      6. Báwo ni àwọn ènìyàn Júdà kò ṣe fòye hùwà?

      6 Níwọ̀n bí irú àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ báyìí ti wọ́pọ̀ gan-an lọ́jọ́ Aísáyà, ohun tí Jèhófà ń sọ yéni, pé: Bí ẹranko lásánlàsàn bá lè dá ọ̀gá rẹ̀ mọ̀, tó sì mọ ibùjẹ òun fúnra rẹ̀, kí wá ni àwíjàre àwọn ènìyàn Júdà fún fífi tí wọ́n fi Jèhófà sílẹ̀? Lóòótọ́, wọn “kò hùwà lọ́nà òye.” Àfi bíi pé wọn kò mọ̀ rárá pé ọwọ́ Jèhófà ni aásìkí àti ìwàláàyè àwọn wà. Ní tòótọ́, àánú ló sún Jèhófà tó ṣì fi ń pe àwọn ará Júdà wọ̀nyẹn ní “àwọn ènìyàn mi”!

      7. Àwọn ọ̀nà wo ni a lè gbà fi hàn pé a mọrírì àwọn ìpèsè Jèhófà?

      7 Ẹ má ṣe jẹ́ ká hu ìwà àìlóye láé, nípa kíkùnà láti fi ìmọrírì hàn fún gbogbo ohun tí Jèhófà ti ṣe fún wa! Kàkà bẹ́ẹ̀, ṣe ló yẹ ká ṣàfarawé olórin náà, Dáfídì, tó sọ pé: “Ṣe ni èmi yóò máa fi gbogbo ọkàn-àyà mi gbé ọ lárugẹ, Jèhófà; èmi yóò máa polongo gbogbo iṣẹ́ àgbàyanu rẹ.” (Sáàmù 9:1) Bíbá tí a bá ń bá a lọ láti gba ìmọ̀ Jèhófà sínú ni yóò fún wa níṣìírí láti ṣe èyí, nítorí Bíbélì sọ pé “ìmọ̀ Ẹni Mímọ́ Jù Lọ sì ni ohun tí òye jẹ́.” (Òwe 9:10) Bí a bá ń ṣàṣàrò lórí àwọn ìbùkún Jèhófà lójoojúmọ́, ìyẹn ni yóò ràn wá lọ́wọ́ láti kún fún ọpẹ́, kí á má sì rí Baba wa ọ̀run fín. (Kólósè 3:15) Jèhófà sọ pé: “Ẹni tí ń rú ìdúpẹ́ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ rẹ̀ ni ó ń yìn mí lógo; àti ní ti ẹni tí ń pa ọ̀nà tí a là sílẹ̀ mọ́, dájúdájú, èmi yóò jẹ́ kí ó rí ìgbàlà láti ọwọ́ Ọlọ́run.”—Sáàmù 50:23.

  • Bàbá Kan Àtàwọn Ọlọ̀tẹ̀ Ọmọ Rẹ̀
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
    • a Nínú ọ̀ràn yìí, ìjọba Júdà tó jẹ́ ẹ̀yà méjì ni a pè ní “Ísírẹ́lì.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́