-
Jèhófà JọbaÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
13, 14. (a) Àwọn òfin wo ni Jèhófà ṣe lórí ọ̀ràn ìkórè? (b) Báwo ni Aísáyà ṣe lo àwọn òfin tó wà nípa ọ̀ràn ìkórè láti fi ṣàpèjúwe bí àwọn kan yóò ṣe la ìdájọ́ Jèhófà já? (d) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àkókò ìdẹwò tó bani nínú jẹ́ ń bọ̀, kí làwọn olóòótọ́ ní Júdà mọ̀ dájú pé ó ń bẹ níwájú fún àwọn?
13 Ńṣe làwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa ń fi ọ̀pá lu igi ólífì kí èso rẹ̀ lè já bọ́ tí wọ́n bá ń kórè rẹ̀. Òfin Ọlọ́run wá kà á léèwọ̀ pé wọn kò gbọ́dọ̀ padà gun igi rẹ̀ láti ká èso tó bá ṣẹ́ kù sórí rẹ̀. Wọn kò sì gbọ́dọ̀ pèéṣẹ́ ọgbà àjàrà wọn lẹ́yìn ìkórè. Àwọn tálákà lèyí tó bá ṣẹ́ kù lẹ́yìn ìkórè wà fún, ìyẹn ni, “fún àwọn àtìpó, fún àwọn ọmọdékùnrin aláìníbaba àti fún àwọn opó” láti pèéṣẹ́ rẹ̀. (Diutarónómì 24:19-21) Òfin táwọn èèyàn mọ̀ dunjú yìí ni Aísáyà lò láti fi ṣàlàyé ọ̀ràn kan tó dùn mọ́ni, ìyẹn ni pé, àwọn kan yóò la ìdájọ́ Jèhófà tó ń bọ̀ yẹn já, ó ní: “Nítorí pé báyìí ni yóò dà ní àárín ilẹ̀ náà, láàárín àwọn ènìyàn, bí lílu igi ólífì, bí èéṣẹ́ nígbà tí kíkó èso àjàrà jọ bá ti wá sí òpin. Àwọn alára yóò gbé ohùn wọn sókè, wọn yóò máa fi ìdùnnú ké jáde. Dájúdájú, nínú ìlọ́lájù Jèhófà ni wọn yóò ké jáde lọ́nà híhan gan-an-ran láti òkun wá. Ìdí nìyẹn tí wọn yóò fi máa yin Jèhófà lógo ní ẹkùn ilẹ̀ ìmọ́lẹ̀, wọn yóò máa yin orúkọ Jèhófà, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, lógo ní àwọn erékùṣù òkun. Láti ìkángun ilẹ̀ náà, àwọn orin atunilára ń bẹ tí àwa ti gbọ́, pé: ‘Ìṣelóge fún Olódodo!’”—Aísáyà 24:13-16a.
14 Bí èso ṣe máa ń ṣẹ́ kù sórí igi tàbí àjàrà lẹ́yìn ìkórè, bẹ́ẹ̀ làwọn kan ṣe máa ṣẹ́ kù lẹ́yìn ìdájọ́ Jèhófà, ìyẹn àwọn “èéṣẹ́ nígbà tí kíkó èso àjàrà jọ bá ti wá sí òpin.” Wòlíì yìí ti sọ ọ́ ṣáájú, ìyẹn ní Ais 24 ẹsẹ kẹfà, pé ‘ìwọ̀nba kéréje ẹni kíkú sì ṣẹ́ kù.’ Àwọn kan yóò la ìparun Jerúsálẹ́mù àti Júdà já síbẹ̀síbẹ̀, bó ti wù kí iye wọ́n kéré tó, lẹ́yìn náà, àṣẹ́kù yóò tún padà wá láti ìgbèkùn láti máa wá gbé ilẹ̀ náà. (Aísáyà 4:2, 3; 14:1-5) Lóòótọ́, àkókò ìdẹwò tó bani nínú jẹ́ yóò dé bá àwọn ọlọ́kàn títọ́, ṣùgbọ́n ó dájú pé ìdáǹdè àti ayọ̀ ń bẹ níwájú fún wọn. Àwọn tó là á já yìí yóò rí i bí ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ Jèhófà ṣe ń ṣẹ, wọn yóò wá rí i pé wòlíì Ọlọ́run ni Aísáyà jẹ́ lóòótọ́. Ayọ̀ yóò kún inú wọn bí wọ́n ṣe ń rí ìmúṣẹ àwọn àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìmúbọ̀sípò yẹn. Láti ibikíbi tí wọ́n bá fọ́n ká sí, ìbáà jẹ́ inú àwọn erékùṣù Mẹditaréníà níhà Ìwọ̀ Oòrùn, tàbí Bábílónì ní “ẹkùn ilẹ̀ ìmọ́lẹ̀” (ìyẹn ìhà yíyọ oòrùn, tàbí Ìlà Oòrùn), tàbí ọ̀nà jíjìn rere yòówù kó jẹ́, wọn yóò máa yin Ọlọ́run nítorí pé ó dá wọn sí, wọn yóò sì kọrin pé: “Ìṣelóge fún Olódodo!”
-
-
Jèhófà JọbaÀsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 265]
Àwọn kan yóò la ìdájọ́ Jèhófà já, gẹ́gẹ́ bí èso ṣe ń ṣẹ́ kù sórí igi lẹ́yìn ìkórè
-