-
Bàbá Kan Àtàwọn Ọlọ̀tẹ̀ Ọmọ Rẹ̀Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
11, 12. (a) Ṣàlàyé ipò burúkú tí Júdà wà. (b) Èé ṣe tí kò fi yẹ kí àánú Júdà ṣe wá?
11 Lẹ́yìn èyí, Aísáyà wá gbìyànjú láti sọ̀rọ̀ tó lè mú kí àwọn ènìyàn Júdà ronú nípa sísọ irú àìsàn tó ń ṣe wọ́n fún wọn. Ó sọ pé: “Ibo ni ó tún kù tí a ó ti lù yín, ní ti pé ẹ túbọ̀ ń dìtẹ̀ sí i?” Ohun tí Aísáyà ń fi èyí béèrè ni pé: ‘Ṣé ìyà ò tíì jẹ yín tó ni? Kí lẹ ṣe tún fẹ́ máa fìyà jẹ ara yín sí i nípa bíbá ìṣọ̀tẹ̀ yín nìṣó?’ Aísáyà ń bọ́rọ̀ rẹ̀ lọ pé: “Gbogbo orí wà ní ipò àìsàn, gbogbo ọkàn-àyà sì jẹ́ ahẹrẹpẹ. Láti àtẹ́lẹsẹ̀ àní dé orí, kò sí ibì kankan nínú rẹ̀ tí ó dá ṣáṣá.” (Aísáyà 1:5, 6a) Júdà ti di ẹni ìríra, ó di olókùnrùn—ó ń ṣàìsàn nípa tẹ̀mí látorí dé àtẹ́lẹsẹ̀. Àrùn tó ń ṣe é mà kúkú burú o!
12 Ǹjẹ́ ó yẹ kí àánú Júdà ṣe wá? Àgbẹdọ̀! Wọ́n kìlọ̀ gbọnmọgbọnmọ fún gbogbo orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì ní ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún ṣáájú, nípa ohun tí àìgbọràn yóò kó bá wọn. Apá kan ìkìlọ̀ ọ̀hún sọ pé: “Jèhófà yóò fi oówo afòòró-ẹ̀mí kọlù ọ́ lórí eékún méjèèjì àti ojúgun méjèèjì, láti inú èyí tí a kì yóò lè mú ọ lára dá, láti àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ títí dé àtàrí rẹ.” (Diutarónómì 28:35) Lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ, ìyà oríkunkun Júdà ló ń jẹ ẹ́ báyìí. Gbogbo ìyà wọ̀nyí ì bá sì má jẹ àwọn ènìyàn Júdà ká ní wọ́n sáà ṣègbọràn sí Jèhófà ni.
13, 14. (a) Àwọn ọgbẹ́ wo ni wọ́n ti dá sí Júdà lára? (b) Ǹjẹ́ ìyà tó jẹ Júdà mú kó túnnú rò lórí ìwà ìṣọ̀tẹ̀ tó ń hù?
13 Aísáyà ń bá àlàyé lọ lórí ipò aṣeniláàánú tí Júdà wà pé: “Àwọn ọgbẹ́ àti ara bíbó àti ojú ibi tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ nà—a kò mọ́ wọn tàbí kí a dì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi òróró tù wọ́n lójú.” (Aísáyà 1:6b) Oríṣi ìpalára mẹ́ta ni wòlíì náà mẹ́nu kàn níhìn-ín: àwọn ọgbẹ́ (ojúu gígé, bíi kí idà tàbí ọ̀bẹ géni), ara bíbó (kí ara dáranjẹ̀ nítorí nínà), àti ojú ibi tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ nà (ojú ọgbẹ́ yánnayànna, tó jọ pé kò ní lè jiná). Èrò tí ibí yìí ń gbé yọ ni tẹnì kan tí wọ́n ti fi ìyà pá lórí, tí kò síbi tí nǹkan ò bà lára rẹ̀. Júdà ti wó sára lóòótọ́.
14 Ǹjẹ́ Júdà tìtorí bójú rẹ̀ ṣe rí màbo yìí padà sọ́dọ̀ Jèhófà bí? Ó tì o! Júdà dà bí ọlọ̀tẹ̀ tí Òwe 29:1 sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀, pé: “Ènìyàn tí a fi ìbáwí tọ́ sọ́nà léraléra, ṣùgbọ́n tí ó mú ọrùn rẹ̀ le, yóò ṣẹ́ lójijì, kì yóò sì ṣeé mú lára dá.” Ó jọ pé orílẹ̀-èdè yẹn kò ṣeé wò sàn mọ́. Bí Aísáyà ṣe sọ ọ́, àwọn ọgbẹ́ rẹ̀, “a kò mọ́ wọn tàbí kí a dì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi òróró tù wọ́n lójú.”b Lọ́rọ̀ kan ṣá, Júdà rí bí egbò àdáàjinná, tí wọn kò dì, tí ó tóbi yànmànkàn.
15. Àwọn ọ̀nà wo la fi lè dáàbò bo ara wa lọ́wọ́ àìsàn tẹ̀mí?
15 Kí a fi ti Júdà ṣàríkọ́gbọ́n o, pé àwa náà gbọ́dọ̀ ṣọ́ra fún àìsàn tẹ̀mí. Bí àìsàn gidi ṣe lè kọluni lòun náà ṣe lè kọlu ẹnikẹ́ni nínú wa. Àbí, ta ni ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara kò lè bá jà? Ìwọra àti afẹ́ ṣíṣe lè gbà wá lọ́kàn. Nítorí náà, a ní láti tọ́ ara wa láti “fi tẹ̀gàntẹ̀gàn kórìíra ohun burúkú” kí a sì “rọ̀ mọ́ ohun rere.” (Róòmù 12:9) Bákan náà ló yẹ ká máa fi èso ẹ̀mí Ọlọ́run ṣèwà hù lójoojúmọ́. (Gálátíà 5:22, 23) Bí a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, a ó yẹra fún ìyọnu tí Júdà kó sí, ìyẹn dídi ẹni tí àìsàn tẹ̀mí bò láti orí dé àtẹ́lẹsẹ̀.
-
-
Bàbá Kan Àtàwọn Ọlọ̀tẹ̀ Ọmọ Rẹ̀Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
b Àwọn ọ̀rọ̀ Aísáyà fi hàn bí ìṣègùn ṣe rí nígbà ayé tirẹ̀. E. H. Plumptre tó jẹ́ aṣèwádìí lórí Bíbélì sọ pé: “Ńṣe ni wọ́n kọ́kọ́ máa ń gbìyànjú láti ‘fún’ tàbí ‘tẹ’ ojú egbò kíkẹ̀ láti mú kí ọyún rẹ̀ jáde; lẹ́yìn náà, wọn a wá fi àpòpọ̀ egbòogi gbígbóná ‘dì í,’ gẹ́gẹ́ bíi ti Hesekáyà (orí xxxviii. 21 [Ais 38:21]), lẹ́yìn náà, wọn a wá fi òróró atániyẹ́ẹ́ tàbí ìwọ́ra pa á, bóyá wọ́n tún ń lo epo tàbí wáìnì láti fi fọ egbò náà, bó ṣe ṣẹlẹ̀ nínú Lúùkù x. 34 [10:34].”
-