-
‘Kò Sí Olùgbé Kankan Tí Yóò Sọ Pé: “Àìsàn Ń Ṣe Mí”’Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
Ìwòsàn
20. Irú ìwòsàn wo ni àwọn èèyàn Ọlọ́run yóò rí gbà, nígbà wo sì ni?
20 Ìlérí amọ́kànyọ̀ kan ló parí ẹ̀ka àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà yìí, ó ní: “Kò sì sí olùgbé kankan tí yóò sọ pé: ‘Àìsàn ń ṣe mí.’ Àwọn ènìyàn tí ń gbé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ àwọn tí a ti dárí ìṣìnà wọn jì wọ́n.” (Aísáyà 33:24) Ní ìpìlẹ̀, àìsàn tẹ̀mí ni Aísáyà ń sọ nípa rẹ̀, nítorí ọ̀rọ̀ yẹn dá lórí ẹ̀ṣẹ̀, tàbí “ìṣìnà.” Ní ọ̀nà àkọ́kọ́ tí Jèhófà gbà lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí, ṣe ló ṣèlérí pé lẹ́yìn tí orílẹ̀-èdè yẹn bá gba ìdáǹdè kúrò lóko ẹrú Bábílónì, òun yóò wò wọ́n sàn nípa tẹ̀mí. (Aísáyà 35:5, 6; Jeremáyà 33:6; fi wé Sáàmù 103:1-5.) Bó sì ṣe di pé àwọn Júù tó padà bọ̀ wálé rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ wọn àtẹ̀yìnwá gbà, ohun tó kàn tí wọn yóò ṣe ni pé kí wọ́n tún bẹ̀rẹ̀ ìjọsìn mímọ́ gaara ní Jerúsálẹ́mù.
21. Àwọn ọ̀nà wo ni àwọn olùsin Jèhófà òde òní gbà ń rí ìwòsàn gbà nípa tẹ̀mí?
21 Àmọ́ ṣá o, àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà ní ìmúṣẹ tòde òní. Àwọn èèyàn Jèhófà lónìí pẹ̀lú rí ìwòsàn tẹ̀mí gbà bákan náà. Wọ́n ti rí ìdáǹdè gbà kúrò lábẹ́ àwọn ẹ̀kọ́ èké bí àìleèkú ọkàn, Mẹ́talọ́kan, àti iná ọ̀run apáàdì. Wọ́n ń gba ìtọ́sọ́nà nípa ìwà ọmọlúwàbí, èyí tó ń mú kí wọ́n jìnnà sí ìwà ìṣekúṣe gbogbo, tó sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́ láti ṣe ìpinnu tó dára. Ẹ̀wẹ̀, ẹbọ ìràpadà Jésù Kristi ló mú kí wọ́n lè wà ní ipò tó mọ́ lójú Ọlọ́run, kí wọ́n sì ní ẹ̀rí ọkàn tó mọ́. (Kólósè 1:13, 14; 1 Pétérù 2:24; 1 Jòhánù 4:10) Ìwòsàn tẹ̀mí yìí ṣàǹfààní nípa ti ara. Bí àpẹẹrẹ, yíyàgò fún ìṣekúṣe àti yíyàgò fún àwọn ohun tí wọ́n bá fi tábà ṣe, kì í jẹ́ kí àwọn Kristẹni kó àwọn àrùn tó ń bá ìṣekúṣe rìn àti irú àwọn àrùn jẹjẹrẹ kan.—1 Kọ́ríńtì 6:18; 2 Kọ́ríńtì 7:1.
22, 23. (a) Ìmúṣẹ tó pẹtẹrí wo ni Aísáyà 33:24 yóò ní lọ́jọ́ iwájú? (b) Kí ló jẹ́ ìpinnu àwọn olùsìn tòótọ́ lóde òní?
22 Ní àfikún sí i, àwọn ọ̀rọ̀ inú Aísáyà 33:24 yóò ṣẹ lọ́nà tó pẹtẹrí nínú ayé tuntun Ọlọ́run, lẹ́yìn Amágẹ́dọ́nì. Nígbà tí Ìjọba Mèsáyà bá ń ṣàkóso, aráyé yóò gba ìwòsàn ńláǹlà nípa ti ara pa pọ̀ mọ́ ìwòsàn tẹ̀mí tí wọ́n ń gbà. (Ìṣípayá 21:3, 4) Ó dájú pé, kété tí ètò àwọn nǹkan Sátánì bá ti pa run, irú àwọn iṣẹ́ ìyanu tí Jésù ṣe nígbà tó wà lórí ilẹ̀ ayé yóò ṣẹlẹ̀ kárí ayé. Afọ́jú yóò ríran, adití yóò gbọ́ràn, arọ yóò rìn! (Aísáyà 35:5, 6) Èyí ni yóò jẹ́ kí gbogbo àwọn tó bá la ìpọ́njú ńlá já lè kópa nínú iṣẹ́ alárinrin ti sísọ ilẹ̀ ayé di Párádísè.
23 Lẹ́yìn náà, bí àjíǹde bá ti bẹ̀rẹ̀, ó dájú pé ara dídá ṣáṣá làwọn tó bá jíǹde yóò bá jí. Àmọ́ o, bí àǹfààní ìtóye ẹbọ ìràpadà bá ṣe túbọ̀ ń wá sí i làwọn àǹfààní mìíràn nípa ti ara yóò ṣe máa yọjú, títí aráyé yóò fi dé ìjẹ́pípé. Ìgbà yẹn ni àwọn olódodo yóò “wá sí ìyè” ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìtumọ̀ rẹ̀. (Ìṣípayá 20:5, 6) Ní ìgbà yẹn, “Kò . . . sí olùgbé kankan tí yóò sọ pé: ‘Àìsàn ń ṣe mí,’” ì báà jẹ́ nípa tẹ̀mí tàbí nípa ti ara. Áà, ìlérí yìí mà wúni lórí o! Ǹjẹ́ kí gbogbo olùsìn tòótọ́ lónìí pinnu láti wà lára àwọn tí yóò rí ìmúṣẹ rẹ̀!
-
-
‘Kò Sí Olùgbé Kankan Tí Yóò Sọ Pé: “Àìsàn Ń Ṣe Mí”’Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
-
-
[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 353]
Ẹbọ ìràpadà ló mú kí àwọn èèyàn Jèhófà wà ní ipò tó mọ́ lójú rẹ̀
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 354]
Nínú ayé tuntun, ìwòsàn ńláǹlà nípa ti ara yóò wáyé
-