-
Jehofa Ń Fúnni ní Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Àlàáfíà àti Òtítọ́Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | January 1
-
-
“Èmi óò . . . wò wọ́n sàn, èmi óò sì fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́ hàn fún wọn.”—JEREMIAH 33:6.
-
-
Jehofa Ń Fúnni ní Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Àlàáfíà àti Òtítọ́Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | January 1
-
-
3. Ní ìmúṣẹ àwọn ọ̀rọ̀ tí Jehofa tẹnu Jeremiah sọ, àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mánigbàgbé wo ni ó kọ́ Israeli lẹ́kọ̀ọ́ kejì pàtàkì nípa àlàáfíà?
3 Ṣùgbọ́n, kí Jerusalemu tó ṣubú, Jehofa ti ṣí i payá pé, òun ni yóò mú àlàáfíà wá fún Israeli, kì í ṣe Egipti. Ó tipasẹ̀ Jeremiah ṣèlérí pé: “Èmi óò . . . wò wọ́n sàn, èmi óò sì fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà àti òtítọ́ hàn fún wọn. Èmi óò sì mú ìgbèkùn Juda àti ìgbèkùn Israeli padà wá, èmi óò sì gbé wọn ró gẹ́gẹ́ bíi ti ìṣáájú.” (Jeremiah 33:6, 7) Ìlérí Jehofa bẹ̀rẹ̀ sí í ní ìmúṣẹ ní ọdún 539 Ṣáájú Sànmánì Tiwa, nígbà tí a ṣẹ́gun Babiloni, tí a sì fún àwọn ọmọ Israeli tí wọ́n wà nígbèkùn ní òmìnira. (2 Kronika 36:22, 23) Nígbà tí yóò fi di apá ìparí ọdún 537 Ṣáájú Sànmánì Tiwa, fún ìgbà àkọ́kọ́ nínú 70 ọdún, àwùjọ àwọn ọmọ Israeli kan ṣayẹyẹ Àjọ Àgọ́ lórí ilẹ̀ Israeli! Lẹ́yìn àjọ náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í tún tẹ́ḿpìlì Jehofa kọ́. Kí ni ìmọ̀lára wọn nípa èyí? Àkọsílẹ̀ náà sọ pé: “Gbogbo ènìyàn náà sì hó ìhó ńlá, nígbà tí wọ́n ń yin Oluwa, nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Oluwa lélẹ̀.”—Esra 3:11.
-