-
“Jọ̀wọ́, Ṣègbọràn Sí Ohùn Jèhófà”Ọ̀rọ̀ Tí Ọlọ́run Bá Wa Sọ Nípasẹ̀ Jeremáyà
-
-
12. Kí làwọn alàgbà ní láti ṣe nígbà míì láti dáàbò bo ìjọ?
12 Ọ̀pọ̀ àwọn Júù ló tẹ́ńbẹ́lú ìrànlọ́wọ́ tí Jèhófà ń gbìyànjú léraléra láti ṣe fún wọn nípasẹ̀ Jeremáyà. Lónìí bákan náà, ẹni tó dẹ́ṣẹ̀ tó burú jáì lè má ronú pìwà dà, kó wá kọ ìrànlọ́wọ́ táwọn alàgbà fẹ́ ṣe fún un. Nírú ipò bẹ́ẹ̀, àwọn alàgbà ní láti ṣe ohun tí Bíbélì sọ, kí wọ́n yọ ẹlẹ́ṣẹ̀ náà lẹ́gbẹ́ láti dáàbò bo ìjọ. (1 Kọ́r. 5:11-13; wo àpótí tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ “Wọ́n Wà Láìsí Òfin,” lójú ìwé 73.) Àmọ́ ṣé ó wá túmọ̀ sí pé kò sírètí fún onítọ̀hún mọ́ ni, pé kò lè rí ojú rere Jèhófà mọ́ láéláé? Rárá o. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ya ọlọ̀tẹ̀ fún ìgbà pípẹ́; síbẹ̀ Ọlọ́run sọ fún wọn pé: “Ẹ padà, ẹ̀yin ọ̀dàlẹ̀ ọmọ. Èmi yóò mú ipò ìwà ọ̀dàlẹ̀ yín lára dá.” (Jer. 3:22)a Bẹ́ẹ̀ ni o, Jèhófà ní kí àwọn oníwà àìtọ́ pa dà sọ́dọ̀ òun. Ńṣe ló tiẹ̀ dìídì fún wọn nítọ̀ọ́ni pé kí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀.
-
-
“Jọ̀wọ́, Ṣègbọràn Sí Ohùn Jèhófà”Ọ̀rọ̀ Tí Ọlọ́run Bá Wa Sọ Nípasẹ̀ Jeremáyà
-
-
a Ìjọba Ísírẹ́lì tó wà níhà àríwá ni Jèhófà ń bá wí níbí. Àwọn èèyàn ìjọba ẹ̀yà mẹ́wàá yìí ti wà nígbèkùn fún odindi ọgọ́rùn-ún ọdún nígbà tí Jeremáyà jíṣẹ́ yìí fún wọn. Jeremáyà sì sọ pé títí di bóun ṣe ń jíṣẹ́ yẹn, orílẹ̀-èdè yẹn lápapọ̀ ò tíì ronú pìwà dà. (2 Ọba 17:16-18, 24, 34, 35) Àmọ́, ẹnì kọ̀ọ̀kan wọn lè pa dà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, kí wọ́n sì rí ojú rere rẹ̀ bóyá kí wọ́n tiẹ̀ kúrò nígbèkùn pàápàá.
-