ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ṣé Wàá Bá Ọlọ́run Rìn?
    Ilé Ìṣọ́—2005 | November 1
    • 11. Ní ìbámu pẹ̀lú Jeremáyà 6:16, àpèjúwe afúnnilókun wo ni Jèhófà lò láti fi ké sí àwọn èèyàn rẹ̀, àmọ́ báwo ni wọ́n ṣe fèsì?

      11 Ǹjẹ́ a máa ń jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run darí wa dáadáa? Ó dára ká máa sinmẹ̀dọ̀ lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan ká sì máa fi òótọ́ inú yẹ ara wa wò dáadáa. Gbé ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀ yẹ̀ wò, ibẹ̀ kà pé: “Èyí ni ohun tí Jèhófà wí: ‘Ẹ dúró jẹ́ẹ́ ní ọ̀nà, kí ẹ sì rí, ẹ béèrè fún àwọn òpópónà ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn, ibi tí ọ̀nà tí ó dára wà nísinsìnyí; ẹ sì máa rìn ín, kí ẹ sì rí ìdẹ̀rùn fún ọkàn yín.’” (Jeremáyà 6:16) Àwọn ọ̀rọ̀ yìí lè rán wa létí arìnrìn-àjò kan tó dúró ní ìkòríta kan láti béèrè ọ̀nà. Ohun tó jọ èyí nípa tẹ̀mí ló yẹ káwọn èèyàn Jèhófà tí wọ́n jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ní Ísírẹ́lì ṣe. Ó yẹ kí wọ́n wá ọ̀nà tí wọ́n a fi padà sí “àwọn òpópónà ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.” “Ọ̀nà tí ó dára” yẹn ni ọ̀nà táwọn baba ńlá wọn tó jẹ́ olóòótọ́ rìn, orílẹ̀-èdè náà sì ti rìn gbéregbère kúrò ní ọ̀nà náà nítorí ìwà òmùgọ̀ wọn. Ó dunni pé ńṣe làwọn ọmọ Ísírẹ́lì tún ń ṣagídí tí wọn ò tẹ̀lé ìránnilétí onífẹ̀ẹ́ tí Jèhófà fún wọn yìí. Ẹsẹ kan náà yẹn tún ń bá a lọ pé: “Ṣùgbọ́n wọ́n ń wí pé: ‘Àwa kì yóò rìn.’” Àmọ́, lóde òní, àwọn èèyàn Ọlọ́run ń tẹ̀ lé ìmọ̀ràn rere yẹn.

      12, 13. (a) Ọ̀nà wo làwọn ẹni àmì òróró ọmọlẹ́yìn Kristi ti gbà fi ìmọ̀ràn tó wà nínú Jeremáyà 6:16 sílò? (b) Báwo la ṣe lè yẹ ara wa wò nípa bá a ṣe ń rìn lóde òní?

      12 Látìgbà tó ti kù díẹ̀ kí ọ̀rúndún kọkàndínlógún parí làwọn ẹni àmì òróró ọmọlẹ́yìn Kristi ti gbà pé àwọn ni ìmọ̀ràn inú ìwé Jeremáyà 6:16 ń bá wí. Gẹ́gẹ́ bí ẹgbẹ́ kan, wọ́n ti mú ipò iwájú nínú fífi gbogbo ọkàn wọn padà sí “àwọn òpópónà ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.” Wọn ò ṣe bíi ti Kirisẹ́ńdọ̀mù apẹ̀yìndà, ńṣe ni wọ́n ń fi ìṣòtítọ́ tẹ̀ lé “àwọn ọ̀rọ̀ afúnni-nílera” tí Jésù Kristi fi lélẹ̀ táwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ò sì fọwọ́ yẹpẹrẹ mú láti ọ̀rúndún kìíní Sànmánì Kristẹni. (2 Tímótì 1:13) Títí di oní olónìí làwọn ẹni àmì òróró ń ran ara wọn lọ́wọ́, tí wọ́n tún ń ran àwọn “àgùntàn mìíràn” tó jẹ́ alábàákẹ́gbẹ́ wọn lọ́wọ́ láti máa tọ ọ̀nà ìgbésí ayé tó ń fúnni nílera àti ayọ̀, èyí tí Kirisẹ́ńdọ̀mù kùnà láti tọ̀.—Jòhánù 10:16.

      13 Nípa pípèsè oúnjẹ tẹ̀mí ní àkókò tó bẹ́tọ̀ọ́ mu, ẹgbẹ́ ẹrú olóòótọ́ náà ti ran àràádọ́ta ọ̀kẹ́ èèyàn lọ́wọ́ láti rí “àwọn òpópónà ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn,” kí wọ́n lè máa bá Ọlọ́run rìn. (Mátíù 24:45-47) Ǹjẹ́ o wà lára àràádọ́ta ọ̀kẹ́ èèyàn yìí? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, kí lo lè ṣe tó ò fi ní sú lọ láé, ìyẹn ni pé tó ò fi ni dẹni tó ń tọ ọ̀nà ti ara rẹ? Ó bọ́gbọ́n mu kó o máa sinmẹ̀dọ̀ lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan kó o máa ṣàyẹ̀wò ọ̀nà tó ò gbà ń rin ìrìn àjò ìgbésí ayé rẹ. Tó o bá ń ka Bíbélì déédéé àtàwọn ìwé tá a gbé karí Bíbélì, tó o tún ń wà níbi gbogbo ìtòlẹ́sẹẹsẹ táwọn ẹni àmì òróró ń ṣe láti fún wa nítọ̀ọ́ni lónìí, a jẹ́ pé o ti ń gba ẹ̀kọ́ láti máa bá Ọlọ́run rìn nìyẹn. Tó o bá sì ń fi ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀ tẹ̀ lé àwọn ìmọ̀ràn tí wọ́n ń fún ọ, a jẹ́ pé o ti ń bá Ọlọ́run rìn nìyẹn, o sì ń tọ “àwọn òpópónà ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.”

  • Ṣé Wàá Bá Ọlọ́run Rìn?
    Ilé Ìṣọ́—2005 | November 1
    • Àwọn Ìbùkún Wo La Óò Rí Gbà?

      17. Bí a bá rìn ní ọ̀nà Jèhófà, irú “ìdẹ̀rùn” wo la máa rí fún ọkàn wa?

      17 Bíbá Jèhófà Ọlọ́run rìn túmọ̀ sí kéèyàn máa gbé ìgbésí ayé tó lárinrin. Rántí ohun tí Jèhófà ṣèlérí fáwọn èèyàn rẹ̀ nípa wíwá “ọ̀nà tí ó dára” náà. Ó sọ pé: “Ẹ . . . máa rìn ín, kí ẹ sì rí ìdẹ̀rùn fún ọkàn yín.” (Jeremáyà 6:16) Kí ni “ìdẹ̀rùn” yẹn túmọ̀ sí? Ṣé ìgbésí ayé ìdẹ̀rùn tó kún fún fàájì àti afẹ́ ayé ni? Rárá ò. Jèhófà pèsè ohun kan tó dáa gan-an ju ìyẹn lọ, ohun kan tẹ́ni tó lówó jù lọ láyé yìí ò lè ní. Láti rí ìdẹ̀rùn fún ọkàn rẹ túmọ̀ sí kó o ní ìbàlẹ̀ ọkàn, kó o tún ní ayọ̀ àti ìtẹ́lọ́rùn, kó o sì wá rí i pé ò ń ṣe ohun tó tọ́ nípa tẹ̀mí. Irú ìdẹ̀rùn bẹ́ẹ̀ túmọ̀ sí pé ọkàn rẹ á balẹ̀ dáadáa pé o ti yan ọ̀nà ìgbésí ayé tó dára jù lọ. Irú ìbàlẹ̀ ọkàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ ìbùkún tó ṣọ̀wọ́n nínú ayé oníwàhálà yìí!

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́