-
Jèhófà Ni Ìpín MiIlé Ìṣọ́—2011 | September 15
-
-
Àwọn Ọmọ Léfì Lẹ́nì Kọ̀ọ̀kan Ní Jèhófà Gẹ́gẹ́ bí Ìpín Wọn
8. Ṣàlàyé wàhálà tó bá ọmọ Léfì kan tó ń jẹ́ Ásáfù.
8 Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà kan, àwọn ọmọ Léfì ní Jèhófà gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn. Àmọ́, ó gbàfiyèsí pé àwọn kan lára àwọn ọmọ Léfì lo gbólóhùn náà, “Jèhófà ni ìpín mi” láti fi ìfọkànsin wọn fún Ọlọ́run hàn, kí wọ́n sì tún fi hàn pé àwọn gbẹ́kẹ̀ lé e. (Ìdárò 3:24) Ọ̀kan lára irú àwọn ọmọ Léfì bẹ́ẹ̀ jẹ́ akọrin. A máa pè é ní Ásáfù, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ẹnì kan tó wá láti ìdílé Ásáfù, ìyẹn ọmọ Léfì tó jẹ́ aṣáájú àwọn akọrin nígbà ayé Dáfídì Ọba. (1 Kíró. 6:31-43) Nínú Sáàmù 73, a kà pé ìdààmú bá Ásáfù (tàbí ọ̀kan lára àwọn àtọmọdọ́mọ rẹ̀). Ó bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ìlara àwọn ẹni búburú tí wọ́n láásìkí, débi tó fi sọ pé: “Dájúdájú, lásán ni mo wẹ ọkàn-àyà mi mọ́, tí mo sì wẹ ọwọ́ mi ní àìmọwọ́mẹsẹ̀.” Ó ṣe kedere pé ó ti gbàgbé àǹfààní iṣẹ́ ìsìn tó ní; ó sì kùnà láti mọyì bí Jèhófà ṣe jẹ́ ìpín rẹ̀. Ohun tó rí náà kó ìdààmú ọkàn bá a “títí [tó] fi wá sínú ibùjọsìn títóbi lọ́lá ti Ọlọ́run.”—Sm. 73:2, 3, 12, 13, 17.
-
-
Jèhófà Ni Ìpín MiIlé Ìṣọ́—2011 | September 15
-
-
11. Kí ni Jeremáyà béèrè, báwo ló sì ṣe rí ìdáhùn sí ìbéèrè rẹ̀?
11 Wòlíì Jeremáyà ni ọmọ Léfì mìíràn tó gbà pé ‘Jèhófà jẹ́ ìpín òun.’ Ẹ jẹ́ ká ṣe àgbéyẹ̀wò ohun tó fà á tó fi lo gbólóhùn yẹn. Jeremáyà ń gbé ní ìlú Ánátótì, ìyẹn ìlú àwọn ọmọ Léfì kan tó wà lẹ́bàá Jerúsálẹ́mù. (Jer. 1:1) Ó nígbà kan tí nǹkan tojú sú Jeremáyà, tó sì béèrè pé: Kí nìdí táwọn èèyàn búburú fi ń láásìkí tí ìyà sì ń jẹ olódodo? (Jer. 12:1) Lẹ́yìn tó ti kíyè sí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ní Jerúsálẹ́mù àti Júdà, ara rẹ̀ kò gbà á mọ́, ó mú “ẹjọ́” ohun tó rí wá síwájú Ọlọ́run. Jeremáyà mọ̀ pé olódodo ni Jèhófà. Ohun tí Jèhófà mí sí Jeremáyà láti kọ lẹ́yìn ìgbà yẹn àti bí Ọlọ́run ṣe mú àwọn àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ ṣẹ pèsè ìdáhùn tí kò ṣeé já ní koro sí ìbéèrè wòlíì náà. Ní ìbámu pẹ̀lú àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Ọlọ́run, àwọn tó tẹ̀ lé ìtọ́sọ́nà Jèhófà ‘rí ọkàn wọn gbà gẹ́gẹ́ bí ohun ìfiṣèjẹ,’ àmọ́ àwọn ẹni burúkú tó láásìkí kò tẹ́tí sí ìkìlọ̀ Ọlọ́run wọ́n sì ṣègbé.—Jer. 21:9.
12, 13. (a) Kí ló mú kí Jeremáyà polongo pé: “Jèhófà ni ìpín mi,” irú ẹ̀mí wo ló sì ní? (b) Kí nìdí tí gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì fi gbọ́dọ̀ ní ẹ̀mí ìdúródeni?
12 Lẹ́yìn náà, nígbà tí Jeremáyà bojú wo ìlú ìbílẹ̀ rẹ̀ tó ti dahoro, ńṣe ló dà bíi pé ó ń rìn nínú òkùnkùn. Ó wá jọ pé Jèhófà ti mú kó “jókòó . . . bí àwọn ènìyàn tí ó ti kú tipẹ́tipẹ́.” (Ìdárò 1:1, 16; 3:6) Jeremáyà ti sọ fún orílẹ̀-èdè alágídí náà pé kí wọ́n pa dà sọ́dọ̀ Baba wọn ọ̀run, àmọ́ ìwà wọn ti burú débi pé Jèhófà pa Jerúsálẹ́mù àti Júdà run. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Jeremáyà kọ́ ló lẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà, èyí bà á lọ́kàn jẹ́. Àmọ́, bí ọ̀rọ̀ yìí ṣe ba wòlíì yìí lọ́kàn jẹ́ tó, ó rántí bí Ọlọ́run ṣe fi ọ̀pọ̀ àánú hàn. Ó sọ pé Jèhófà ni kò jẹ́ kí “a wá sí òpin wa.” Dájúdájú, Jèhófà máa ń sọ àánú rẹ̀ dọ̀tun ní òròòwúrọ̀! Lẹ́yìn náà ni Jeremáyà wa polongo pé: “Jèhófà ni ìpín mi.” Ó láǹfààní láti máa bá a nìṣó ní sísin Jèhófà gẹ́gẹ́ bíi wòlíì.—Ka Ìdárò 3:22-24.
13 Fún àádọ́rin [70] ọdún, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò ní ní ìlú ìbílẹ̀ rárá. Ìlú wọn á dahoro. (Jer. 25:11) Àmọ́ ọ̀rọ̀ tí Jeremáyà sọ pé “Jèhófà ni ìpín mi” fi hàn pé ó dá a lójú pé Jèhófà máa fi àánú hàn, ìyẹn sì mú kó rí ìdí tó fi gbọ́dọ̀ ní “ẹ̀mí ìdúródeni.” Gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì máa pàdánù ogún wọn, torí náà, ó ṣe pàtàkì pé kí wọ́n ní irú ẹ̀mí tí wòlíì náà ní. Jèhófà nìkan ṣoṣo ló lè ràn wọ́n lọ́wọ́. Lẹ́yìn àádọ́rin [70] ọdún, àwọn èèyàn Ọlọ́run pa dà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn, wọ́n sì ní àǹfààní láti máa sìn ín níbẹ̀.—2 Kíró. 36:20-23.
-