-
“Sàmì sí Iwájú Orí” WọnÌjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
5, 6. Kí la lè sọ nípa àwọn tí wọ́n sàmì sí lórí? (Wo àwòrán tó wà níbẹ̀rẹ̀ orí yìí.)
5 Kí ni ọkùnrin tó ní ìwo yíǹkì náà fẹ́ ṣe? Jèhófà gbé iṣẹ́ pàtàkì kan fún un, ó ní: “Lọ káàkiri ìlú náà, káàkiri Jerúsálẹ́mù, kí o sì sàmì sí iwájú orí àwọn èèyàn tó ń kẹ́dùn, tí wọ́n sì ń kérora torí gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe ní ìlú náà.” Lójú ẹsẹ̀, ó ṣeé ṣe kí Ìsíkíẹ́lì rántí bí àwọn òbí tí wọ́n jẹ́ olóòótọ́ ní Ísírẹ́lì ṣe fi ẹ̀jẹ̀ sàmì sí òkè ẹnu ọ̀nà àtàwọn òpó ilẹ̀kùn wọn, kí àwọn àkọ́bí wọn má bàa pa run. (Ẹ́kís. 12:7, 22, 23) Nínú ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí yìí, ṣé iṣẹ́ kan náà ni àmì ọkùnrin tó gbé ìwo yíǹkì dání yìí ń ṣe, ìyẹn àmì tó ń fi síwájú orí àwọn èèyàn? Ṣé ó túmọ̀ sí pé ẹni tó bá ti ní àmì náà máa la ìparun Jerúsálẹ́mù já?
6 Ìdáhùn ìbéèrè yìí máa ṣe kedere tá a bá wo ohun tó ń mú wọn sàmì yẹn sórí àwọn èèyàn. Iwájú orí àwọn “tó ń kẹ́dùn, tí wọ́n sì ń kérora” torí àwọn ohun ìríra “tí wọ́n ń ṣe ní ìlú náà” ni wọ́n ń sàmì sí. Kí nìyẹn ń sọ fún wa nípa àwọn tí wọ́n sàmì sì lórí? Àkọ́kọ́ ni pé, kì í ṣe torí ìbọ̀rìṣà tí wọ́n ń ṣe nínú tẹ́ńpìlì nìkan ni ẹ̀dùn ọkàn ṣe bá wọn, àmọ́ wọ́n tún kẹ́dùn torí gbogbo ìwà ipá, ìṣekúṣe àti ìwà ìbàjẹ́ tó kúnnú Jerúsálẹ́mù. (Ìsík. 22:9-12) Yàtọ̀ síyẹn, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé wọn ò fi bọ́rọ̀ náà ṣe rí lára wọn pa mọ́. Ó dájú pé ọ̀rọ̀ ẹnu àti ìwà àwọn olóòótọ́ èèyàn yìí fi hàn pé wọ́n kórìíra àwọn ohun tó ń wáyé nílẹ̀ náà àti pé ìjọsìn mímọ́ ló jẹ wọ́n lógún. Jèhófà máa ṣàánú àwọn ẹni yíyẹ yìí, ó sì máa dá ẹ̀mí wọn sí.
-
-
“Sàmì sí Iwájú Orí” WọnÌjọsìn Mímọ́ Jèhófà Ti Pa Dà Bọ̀ Sípò!
-
-
9, 10. Àwọn wo ló wà lára àwọn olóòótọ́ èèyàn tó la ìparun Jerúsálẹ́mù já? Kí la sì lè sọ nípa wọn?
9 Ka 2 Kíróníkà 36:17-20. Àsọtẹ́lẹ̀ Ìsíkíẹ́lì ṣẹ lọ́dún 607 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni nígbà tí àwọn ọmọ ogun Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù àti tẹ́ńpìlì rẹ̀ run. Jèhófà fi Bábílónì ṣe ohun èlò, bí ‘ife ní ọwọ́ Jèhófà’ tó fi da ìyà sórí àwọn èèyàn Jerúsálẹ́mù tí wọ́n ya aláìṣòótọ́. (Jer. 51:7) Ṣé gbogbo èèyàn ìlú náà ni wọ́n pa run? Rárá o. Ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn kan wà tí àwọn ará Bábílónì kò ní pa run.—Jẹ́n. 18:22-33; 2 Pét. 2:9.
10 Àwọn olóòótọ́ èèyàn kan la ìparun náà já, lára wọn ni àwọn ọmọ Rékábù, Ebedi-mélékì ará Etiópíà, Jeremáyà wòlíì àti Bárúkù akọ̀wé rẹ̀. (Jer. 35:1-19; 39:15-18; 45:1-5) Ìran tí Ìsíkíẹ́lì rí jẹ́ ká rí i pé àwọn tá a mẹ́nu bà yìí á ti máa ‘kẹ́dùn, wọ́n á sì máa kérora torí gbogbo ohun ìríra’ tí wọ́n ń ṣe ní Jerúsálẹ́mù. (Ìsík. 9:4) Ṣáájú ìparun yẹn, wọ́n ti fi hàn kedere pé àwọn ò nífẹ̀ẹ́ sí ìwàkiwà àti pé ìjọsìn mímọ́ ló jẹ àwọn lógún, èyí ló jẹ́ kí wọ́n lè la ìparun yẹn já.
11. Àwọn wo ni ọkùnrin tó ní ìwo yíǹkì àtàwọn ọkùnrin mẹ́fà tí wọ́n mú ohun ìjà tí wọ́n fi ń fọ́ nǹkan dání ṣàpẹẹrẹ?
11 Ṣé àmì tá a lè fojú rí ni wọ́n fi síwájú orí àwọn olóòótọ́ èèyàn yẹn? Kò sí àkọsílẹ̀ tó fi hàn pé Ìsíkíẹ́lì tàbí wòlíì èyíkéyìí lọ káàkiri Jerúsálẹ́mù, tó sì wá ń sàmì tá a lè fojú rí síwájú orí àwọn olóòótọ́ èèyàn. Ó ṣe kedere nígbà náà pé ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lókè ọ̀run ni Ìsíkíẹ́lì rí nínú ìran tó fi sàsọtẹ́lẹ̀ yìí, kì í ṣohun táwa èèyàn lè fojú rí. Ọkùnrin tó ní ìwo yíǹkì akọ̀wé àtàwọn ọkùnrin mẹ́fà tí wọ́n mú ohun ìjà tí wọ́n fi ń fọ́ nǹkan dání nínú ìran náà ṣàpẹẹrẹ àwọn áńgẹ́lì olóòótọ́ tí Jèhófà dá sí ọrun, tí wọ́n máa ń múra tán nígbà gbogbo láti jíṣẹ́ tó bá rán wọn. (Sm. 103:20, 21) Ó dájú pé Jèhófà lo àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ láti mú ìdájọ́ rẹ̀ ṣẹ sórí àwọn èèyàn Jerúsálẹ́mù aláìṣòótọ́. Bí ẹni ń sàmì síwájú orí àwọn tó máa là á já, àwọn áńgẹ́lì náà rí i dájú pé gbogbo èèyàn kọ́ ló pa run, wọ́n dá ẹ̀mí àwọn kan sí.
-