-
A Ṣí Àkókò Dídé Mèsáyà PayáKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
23. Èé ṣe tí “Mèsáyà Aṣáájú” fi ní láti kú, ìgbà wo ni èyí yóò sì ṣẹlẹ̀?
23 Kí ni a ó ṣe láṣeparí nínú ọ̀sẹ̀ àádọ́rin? Gébúrẹ́lì sọ pé sáà “àádọ́rin ọ̀sẹ̀” ni a ti pinnu “láti lè mú ìrélànàkọjá kásẹ̀ nílẹ̀, àti láti pa ẹ̀ṣẹ̀ rẹ́ kúrò, àti láti ṣe ètùtù nítorí ìṣìnà, àti láti mú òdodo wá fún àkókò tí ó lọ kánrin, àti láti fi èdìdì tẹ ìran àti wòlíì, àti láti fòróró yan Ibi Mímọ́ Nínú Àwọn Ibi Mímọ́.” Láti lè ṣàṣeparí èyí, “Mèsáyà Aṣáájú” náà ní láti kú. Nígbà wo? Gébúrẹ́lì sọ pé: “Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjì-lé-lọ́gọ́ta náà, a óò ké Mèsáyà kúrò, kì yóò sì sí nǹkan kan fún un. . . . Yóò sì mú májẹ̀mú máa ṣiṣẹ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan; àti ní ìdajì ọ̀sẹ̀ náà yóò mú kí ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ ẹ̀bùn kásẹ̀ nílẹ̀.” (Dáníẹ́lì 9:26a, 27a) Àkókò tí ọ̀ràn dórí kókó ni “ìdajì ọ̀sẹ̀ náà,” ìyẹn ni, ní agbedeméjì ọ̀sẹ̀ ọdún tí ó kẹ́yìn.
24, 25. (a) Gẹ́gẹ́ bí a ṣe sọ tẹ́lẹ̀, ìgbà wo ni Kristi kú, kí sì ni ikú àti àjíǹde rẹ̀ mú wá sí ìparí? (b) Kí ni ikú Jésù mú kí ó ṣeé ṣe?
24 Iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí Jésù Kristi ṣe láàárín àwọn ènìyàn bẹ̀rẹ̀ ní apá ìparí ọdún 29 Sànmánì Tiwa, ó sì gba ọdún mẹ́ta àti ààbọ̀. Gẹ́gẹ́ bí a ṣe sọ ọ́ tẹ́lẹ̀, ní apá ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 33 Sànmánì Tiwa, a “ké” Kristi “kúrò” nígbà tí ó kú lórí òpó igi oró, ní fífi ìwàláàyè rẹ̀ ṣe ìràpadà fún aráyé. (Aísáyà 53:8; Mátíù 20:28) Ìwúlò fífi ẹran àti àwọn ọrẹ ẹbọ tí Òfin kà sílẹ̀ rúbọ dópin nígbà tí Jésù tí a jí dìde gbé ìtóye ẹbọ ìwàláàyè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tọ Ọlọ́run lọ ní ọ̀run. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn àlùfáà Júù ṣì ń bá a lọ láti rú ẹbọ títí tí a fi pa tẹ́ńpìlì Jerúsálẹ́mù run ní ọdún 70 Sànmánì Tiwa, Ọlọ́run kò tẹ́wọ́ gba irú àwọn ẹbọ bẹ́ẹ̀ mọ́. A ti fi ẹbọ tí ó dára jù ú lọ rọ́pò rẹ̀, ọ̀kan tí a kò ní padà tún ṣe mọ́ láé. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “[Kristi] rú ẹbọ kan ṣoṣo fún ẹ̀ṣẹ̀ títí lọ fáàbàdà . . . Nítorí nípa ọrẹ ẹbọ ìrúbọ kan ṣoṣo ni òun fi sọ àwọn tí a ń sọ di mímọ́ di pípé títí lọ fáàbàdà.”—Hébérù 10:12, 14.
-
-
A Ṣí Àkókò Dídé Mèsáyà PayáKíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì
-
-
26. (a) Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti mú májẹ̀mú Òfin kúrò, májẹ̀mú wo ni a mú kí ó ‘máa ṣiṣẹ́ fún ọ̀sẹ̀ kan’? (b) Kí ní ṣẹlẹ̀ ní òpin ọ̀sẹ̀ àádọ́rin náà?
26 Bí Jèhófà ṣe mú májẹ̀mú Òfin kúrò nípasẹ̀ ikú Kristi ní ọdún 33 Sànmánì Tiwa nìyẹn. Ọ̀nà wo ni a wá fi lè sọ pé Mèsáyà “mú májẹ̀mú máa ṣiṣẹ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan”? Nítorí pé ó mú kí májẹ̀mú Ábúráhámù máa bá iṣẹ́ lọ ni. Títí tí ọ̀sẹ̀ àádọ́rin fi parí, àwọn irú ọmọ Ábúráhámù tí wọ́n jẹ́ Hébérù ni Ọlọ́run nawọ́ àwọn ìbùkún májẹ̀mú yẹn sí. Ṣùgbọ́n ní òpin “àádọ́rin ọ̀sẹ̀” ọdún náà, ní ọdún 36 Sànmánì Tiwa, àpọ́sítélì Pétérù wàásù fún Kọ̀nílíù, ọkùnrin ará Ítálì kan, tí ó jẹ́ olùfọkànsìn àti agbo ilé rẹ̀, àti àwọn Kèfèrí mìíràn. Láti ọjọ́ náà lọ ni a sì ti bẹ̀rẹ̀ sí wàásù ìhìn rere láàárín àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè.—Ìṣe 3:25, 26; 10:1-48; Gálátíà 3:8, 9, 14.
-