-
“Ọba Àríwá” Ní Àkókò Òpin YìíIlé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020 | May
-
-
8. Ta ni ọba gúúsù láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí?
8 Nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní, orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà àti ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì jọ pawọ́ pọ̀ ja ogun náà, ìyẹn sì mú kí wọ́n lágbára gan-an. Àsìkò yẹn ni wọ́n di ohun tá a mọ̀ lónìí sí Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà. Bí Dáníẹ́lì ṣe sọ tẹ́lẹ̀, ọba yìí ní “ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ ogun tó lágbára lọ́nà àrà ọ̀tọ̀.” (Dán. 11:25) Láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, Agbára Ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ni ọba gúúsù.c Tó bá rí bẹ́ẹ̀, ta wá ni ọba àríwá?
ỌBA ÀRÍWÁ TÚN FARA HÀN
9. Ìgbà wo ni ọba àríwá tún fara hàn, báwo sì lọ̀rọ̀ tó wà nínú Dáníẹ́lì 11:25 ṣe nímùúṣẹ?
9 Ní 1871, ìyẹn ọdún kan lẹ́yìn tí Russell àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ dá àwùjọ tí wọ́n jọ ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì sílẹ̀, ọba àríwá tún fara hàn. Lọ́dún yẹn, Otto von Bismarck pa àwọn ìlú mélòó kan tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ara wọn pọ̀, ó sì pè é ní orílẹ̀-èdè Jámánì. Ọba Wilhelm Kìíní tó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ Prussia ni olú ọba àkọ́kọ́, ó sì yan Bismarck ṣe olórí ìjọba àkọ́kọ́.d Bọ́dún ṣe ń gorí ọdún, orílẹ̀-èdè Jámánì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso àwọn orílẹ̀-èdè míì ní Áfíríkà àtàwọn erékùṣù tó wà ní Òkun Pàsífíìkì, ó sì ń wá bó ṣe máa lágbára ju ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì lọ. (Ka Dáníẹ́lì 11:25.) Ilẹ̀ Jámánì ní ẹgbẹ́ ológun tó lágbára, kódà òun ni orílẹ̀-èdè kejì táwọn ọmọ ogun ojú omi rẹ̀ pọ̀ jù lọ láyé. Àwọn ẹgbẹ́ ológun yìí ni Jámánì lò láti bá àwọn ọ̀tá rẹ̀ jà nígbà Ogun Àgbáyé Kìíní.
10. Báwo ni Dáníẹ́lì 11:25b, 26 ṣe nímùúṣẹ?
10 Dáníẹ́lì wá sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí ilẹ̀ Jámánì àtàwọn ẹgbẹ́ ológun rẹ̀. Àsọtẹ́lẹ̀ yẹn jẹ́ kó ṣe kedere pé ọba àríwá kò “ní dúró.” Kí nìdí? “Torí wọ́n máa gbèrò ibi sí i. Àwọn tó ń jẹ oúnjẹ aládùn rẹ̀ máa fa ìṣubú rẹ̀.” (Dán. 11:25b, 26a) Lásìkò tí Dáníẹ́lì gbáyé, lára àwọn tó ń jẹ “oúnjẹ aládùn tí ọba ń jẹ” ni àwọn ìjòyè tó ń “bá ọba ṣiṣẹ́.” (Dán. 1:5) Àwọn wo gan-an ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀? Àwọn èèyàn jàǹkàn-jàǹkàn tó wà nínú ìjọba ilẹ̀ Jámánì ni, títí kan àwọn olórí ogun àtàwọn agbaninímọ̀ràn ìjọba. Àwọn yìí ló fa ìṣubú ilẹ̀ ọba náà.e Yàtọ̀ sí pé àsọtẹ́lẹ̀ yẹn sọ ohun tó máa fa ìṣubú ilẹ̀ ọba náà, ó tún sọ àbájáde ogun tó wáyé láàárín òun àti ọba gúúsù. Ohun tí àsọtẹ́lẹ̀ náà sọ nípa ọba àríwá ni pé: “Ní ti àwọn ọmọ ogun rẹ̀, a máa gbá wọn lọ, a sì máa pa ọ̀pọ̀ nínú wọn run.” (Dán. 11:26b) Bí àsọtẹ́lẹ̀ náà ṣe sọ ló rí, àwọn ọ̀tá gbá àwọn ọmọ ogun ilẹ̀ Jámánì lọ, wọ́n sì “pa ọ̀pọ̀ nínú wọn run.” Tá a bá fi wéra pẹ̀lú àwọn ogun tó ti wáyé ṣáájú ìgbà yẹn, ogun yẹn ló tíì burú jù nínú ìtàn ẹ̀dá.
-
-
“Ọba Àríwá” Ní Àkókò Òpin YìíIlé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020 | May
-
-
e Ọ̀pọ̀ nǹkan tí wọ́n ṣe ló jẹ́ kí ilẹ̀ ọba náà tètè ṣubú. Bí àpẹẹrẹ, wọ́n pa dà lẹ́yìn olú ọba náà, wọ́n tú àṣírí bí àwọn ṣe fẹ́ ja ogun yẹn fáwọn ọ̀tá, wọ́n sì fipá mú olú ọba náà láti fipò rẹ̀ sílẹ̀.
-