-
“Ọba Àríwá” Ní Àkókò Òpin YìíIlé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020 | May
-
-
10. Báwo ni Dáníẹ́lì 11:25b, 26 ṣe nímùúṣẹ?
10 Dáníẹ́lì wá sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí ilẹ̀ Jámánì àtàwọn ẹgbẹ́ ológun rẹ̀. Àsọtẹ́lẹ̀ yẹn jẹ́ kó ṣe kedere pé ọba àríwá kò “ní dúró.” Kí nìdí? “Torí wọ́n máa gbèrò ibi sí i. Àwọn tó ń jẹ oúnjẹ aládùn rẹ̀ máa fa ìṣubú rẹ̀.” (Dán. 11:25b, 26a) Lásìkò tí Dáníẹ́lì gbáyé, lára àwọn tó ń jẹ “oúnjẹ aládùn tí ọba ń jẹ” ni àwọn ìjòyè tó ń “bá ọba ṣiṣẹ́.” (Dán. 1:5) Àwọn wo gan-an ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀? Àwọn èèyàn jàǹkàn-jàǹkàn tó wà nínú ìjọba ilẹ̀ Jámánì ni, títí kan àwọn olórí ogun àtàwọn agbaninímọ̀ràn ìjọba. Àwọn yìí ló fa ìṣubú ilẹ̀ ọba náà.e Yàtọ̀ sí pé àsọtẹ́lẹ̀ yẹn sọ ohun tó máa fa ìṣubú ilẹ̀ ọba náà, ó tún sọ àbájáde ogun tó wáyé láàárín òun àti ọba gúúsù. Ohun tí àsọtẹ́lẹ̀ náà sọ nípa ọba àríwá ni pé: “Ní ti àwọn ọmọ ogun rẹ̀, a máa gbá wọn lọ, a sì máa pa ọ̀pọ̀ nínú wọn run.” (Dán. 11:26b) Bí àsọtẹ́lẹ̀ náà ṣe sọ ló rí, àwọn ọ̀tá gbá àwọn ọmọ ogun ilẹ̀ Jámánì lọ, wọ́n sì “pa ọ̀pọ̀ nínú wọn run.” Tá a bá fi wéra pẹ̀lú àwọn ogun tó ti wáyé ṣáájú ìgbà yẹn, ogun yẹn ló tíì burú jù nínú ìtàn ẹ̀dá.
-
-
“Ọba Àríwá” Ní Àkókò Òpin YìíIlé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020 | May
-
-
e Ọ̀pọ̀ nǹkan tí wọ́n ṣe ló jẹ́ kí ilẹ̀ ọba náà tètè ṣubú. Bí àpẹẹrẹ, wọ́n pa dà lẹ́yìn olú ọba náà, wọ́n tú àṣírí bí àwọn ṣe fẹ́ ja ogun yẹn fáwọn ọ̀tá, wọ́n sì fipá mú olú ọba náà láti fipò rẹ̀ sílẹ̀.
-