-
“Ẹ Pòkìkí Èyí Láàárín Àwọn Orílẹ̀-èdè”Máa Fi Ọjọ́ Jèhófà Sọ́kàn
-
-
Kí ni wàá ṣe tó o bá gbọ́ tí kìnnìún kan ń ké ramúramù?
1. Kí nìdí tá a fi lè fi ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ fún wòlíì rẹ̀ wé ìbúramúramù kìnnìún?
ǸJẸ́ o ti gbọ́ ìbúramúramù kìnnìún rí? Wọ́n sọ pé igbe rẹ̀ máa ń rinlẹ̀ ju ariwo ẹ̀rọ tí wọ́n fi ń fọ́ òkúta tàbí tí wọ́n fi ń fọ́ kọnkéré lọ. Tó o bá gbọ́ igbe kìnnìún nítòsí ilé rẹ láàjìn òru, kí ni wàá ṣe? Ó dájú pé ojú ẹsẹ̀ ni wàá ṣe ohun tó yẹ. Ámósì, ọ̀kan lára àwọn wòlíì méjìlá tá à ń gbé ọ̀rọ̀ wọn yẹ̀ wò, lo àfiwé kan bí èyí, ó ní: “Kìnnìún kan wà tí ó ti ké ramúramù! Ta ni kì yóò fòyà? Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ tìkára rẹ̀ ti sọ̀rọ̀! Ta ni kì yóò sọ tẹ́lẹ̀?” (Ámósì 3:3-8) Tó o bá gbọ́ tí Jèhófà fúnra rẹ̀ sọ̀rọ̀, ǹjẹ́ o ò ní ṣe bíi ti Ámósì? Ńṣe ló bẹ̀rẹ̀ sí í sọ tẹ́lẹ̀ lòdì sí ìjọba ẹ̀yà mẹ́wàá Ísírẹ́lì lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀.
-
-
“Ẹ Pòkìkí Èyí Láàárín Àwọn Orílẹ̀-èdè”Máa Fi Ọjọ́ Jèhófà Sọ́kàn
-
-
3. Báwo lo ṣe lè ṣe iṣẹ́ tó jọ tàwọn wòlíì tá à ń kẹ́kọ̀ọ́ ìwé wọn?
3 Ǹjẹ́ òótọ́ lò ń ṣe iṣẹ́ kan tó jọ tàwọn wòlíì náà? O lè máà gbọ́ ìbúramúramù kìnnìún ní ti pé kí Jèhófà mí sí ọ ní tààràtà. Àmọ́, nípasẹ̀ Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀, o tí gbọ́ ìhìn kánjúkánjú nípa ọjọ́ Jèhófà tó rọ̀ dẹ̀dẹ̀. Gẹ́gẹ́ bá a ṣe mẹ́nu kàn án ní Orí Kìíní ìwé yìí, ọ̀rọ̀ náà “wòlíì” ní ìtumọ̀ tó pọ̀ díẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé o lè máà jẹ́ wòlíì lọ́nà tí Ámósì àtàwọn mìíràn láyé ọjọ́un gbà jẹ́ wòlíì, o lè sọ̀rọ̀ nípa ọjọ́ ọ̀la. Lọ́nà wo? O lè kéde àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó o ti kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀ nínú Ìwé Mímọ́, èyí tí ìwé àwọn wòlíì méjìlá náà jẹ́ ara rẹ̀. Ìsinsìnyí gan-an ló sì yẹ kó o kéde rẹ̀.
-