-
Ojú Tí Jèhófà Fi Ń wo Àwọn Ẹlòmíràn Ni Kó O Máa Fi Wò Wọ́nIlé Ìṣọ́—2003 | March 15
-
-
5. Iṣẹ́ wo la gbé lé Jónà lọ́wọ́, kí ló sì ṣe?
5 Jónà sìn gẹ́gẹ́ bíi wòlíì fún ìjọba àríwá Ísírẹ́lì nígbà ayé Jèróbóámù Ọba Kejì tó jẹ́ ọmọkùnrin Jèhóáṣì. (2 Àwọn Ọba 14:23-25) Lọ́jọ́ kan, Jèhófà pàṣẹ fún Jónà láti fi Ísírẹ́lì sílẹ̀ kó sì rìnrìn àjò lọ sí Nínéfè, olú ìlú Ilẹ̀ Ọba Ásíríà alágbára. Iṣẹ́ wo la yàn fún un? Iṣẹ́ náà ni pé kó lọ kìlọ̀ fáwọn olùgbé ibẹ̀ pé a ó pa ìlú ńlá wọn alágbára run. (Jónà 1:1, 2) Dípò kí Jónà ṣe ohun tí Ọlọ́run rán an yìí, ńṣe ló fẹsẹ̀ fẹ! Ó lọ wọ ọkọ̀ òkun tó ń lọ sí Táṣíṣì, ìyẹn ìlú kan tó jìnnà gan-an sí Nínéfè.—Jónà 1:3.
-
-
Ojú Tí Jèhófà Fi Ń wo Àwọn Ẹlòmíràn Ni Kó O Máa Fi Wò Wọ́nIlé Ìṣọ́—2003 | March 15
-
-
9. Nígbà tí ìjì líle fẹ́ gbẹ̀mí àwọn afòkunṣọ̀nà, àwọn ànímọ́ wo ni Jónà fi hàn?
9 Kí Jónà má bàá ṣègbọràn sí àṣẹ Jèhófà, ó wọ ọkọ̀ òkun tó gbé e lọ síbi tó jìnnà réré sí ibi iṣẹ́ tá a yàn fún un. Síbẹ̀síbẹ̀, Jèhófà ò kọ ìránṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ tàbí kó fi ẹlòmíràn rọ́pò rẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni Jèhófà pe orí Jónà wálé. Ọlọ́run mú kí ìjì líle kan bẹ̀rẹ̀ sí jà lórí òkun. Ìgbì omi náà ń gbé ọkọ̀ tí Jónà wà nínú rẹ̀ káàkiri. Ó kù díẹ̀ káwọn aláìmọwọ́mẹsẹ̀ pàdánù ẹ̀mí wọn, Jónà ló sì ṣokùnfà gbogbo rẹ̀! (Jónà 1:4) Kí ni kí Jónà wá ṣe? Nítorí pé Jónà ò fẹ́ káwọn atukọ̀ ojú omi tí wọ́n wà lókè ọkọ náà pàdánù ẹ̀mí wọn, ó sọ fún wọn pé: “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì jù mí sínú òkun, òkun yóò sì pa rọ́rọ́ fún yín.” (Jónà 1:12) Kò sóhun tó lè mú kí Jónà ronú pé nígbà táwọn afòkunṣọ̀nà bá ju òun sómi, Jèhófà yóò ṣe ọ̀nà àbájáde fún òun. (Jónà 1:15) Bó ti wù kó rí, Jónà múra tán láti fi ẹ̀mí ara rẹ̀ jinkú káwọn atukọ̀ ojú omi náà má bàa ṣègbé. Ǹjẹ́ a rí ànímọ́ ìgboyà, ìrẹ̀lẹ̀ àti ìfẹ́ tó fi hàn níhìn-ín?
-