-
Àwọn Ìránṣẹ́ Jèhófà Ní Ìrètí Tòótọ́Ilé Ìṣọ́—2003 | August 15
-
-
19, 20. Báwo ni nǹkan ṣe rí fún àwọn Júù tó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà?
19 Àmọ́ ṣá o, ìrètí àwọn tó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà kò ní já sófo. Jèhófà kò ní da àwọn májẹ̀mú tó bá Ábúráhámù àti Dáfídì dá, ó sì fi àánú hàn sí àwọn bíi Míkà tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, tí wọ́n sì ń kẹ́dùn lórí bí àwọn èèyàn ṣe ya ara wọn nípa sí Ọlọ́run. Tìtorí irú àwọn èèyàn bẹ́ẹ̀ ni ìmúpadàbọ̀sípò ṣe wáyé nígbà tí àkókò tó lójú Ọlọ́run.
20 Ìyẹn wáyé lọ́dún 537 ṣááju Sànmánì Tiwa, lẹ́yìn tí Bábílónì ṣubú àti nígbà tí àṣẹ́kù àwọn Júù padà bọ̀ wálé. Àkókò yẹn ni ọ̀rọ̀ Míkà 2:12 ní ìmúṣẹ rẹ̀ àkọ́kọ́. Jèhófà sọ pé: “Èmi yóò kó Jékọ́bù jọ dájúdájú, gbogbo yín; láìsí àní-àní, èmi yóò kó àwọn tí ó ṣẹ́ kù nínú Ísírẹ́lì jọpọ̀. Èmi yóò gbé wọn kalẹ̀ ní ìṣọ̀kan, bí agbo ẹran nínú ọgbà ẹran, bí agbo ẹran ọ̀sìn láàárín pápá ìjẹko rẹ̀; ibẹ̀ yóò sì kún fún ariwo àwọn ènìyàn.” Jèhófà mà nífẹ̀ẹ́ o! Lẹ́yìn tó bá àwọn èèyàn rẹ̀ wí tán, ó jẹ́ káwọn tó ṣẹ́ kù padà wá sin òun ní ilẹ̀ tó fún àwọn baba ńlá wọn.
-
-
Àwọn Ìránṣẹ́ Jèhófà Ní Ìrètí Tòótọ́Ilé Ìṣọ́—2003 | August 15
-
-
22. Àwọn ẹgbẹ́ méjì wo ló gbé ìrètí wọn ka Ìjọba Ọlọ́run?
22 Ní ọdún 1919, àwọn Kristẹni olóòótọ́ tí wọ́n jẹ́ ẹni àmì òróró ya ara wọn sọ́tọ̀ pátápátá kúrò lọ́dọ̀ Kirisẹ́ńdọ̀mù, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí kéde ìhìn rere Ìjọba náà fún gbogbo orílẹ̀-èdè. (Mátíù 24:14) Àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn tó jẹ́ Ísírẹ́lì tẹ̀mí ni wọ́n kọ́kọ́ wá kàn. Ẹ̀yìn ìyẹn ni “àwọn àgùntàn mìíràn” wá dara pọ̀ mọ́ wọn, tí ẹgbẹ́ méjèèjì sì wá di “agbo kan, olùṣọ́ àgùntàn kan.” (Jòhánù 10:16) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ti ń sin Ọlọ́run ní igba ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n [234] ilẹ̀ báyìí, síbẹ̀ gbogbo àwọn olóòótọ́ olùjọ́sìn fún Jèhófà wọ̀nyí ló wà “ní ìṣọ̀kan” ní ti tòótọ́. Àti pé nísinsìnyí, agbo àgùntàn náà ti “kún fún ariwo àwọn ènìyàn,” ìyẹn àwọn ọkùnrin, obìnrin, ọmọdé àti àgbà. Wọn ò gbé ìrètí wọn ka ètò àwọn nǹkan yìí, bí kò ṣe Ìjọba Ọlọ́run, èyí tí yóò mú Párádísè padà bọ̀ sórí ilẹ̀ ayé láìpẹ́.
-