ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Báwo Ni Àkókò Tó Ṣẹ́ Kù Fún Àwọn Olubi Ti Pọ̀ Tó?
    Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
    • Gbára Dì fún Àwọn Ọ̀rọ̀ Tí Jèhófà Tún Fẹ́ Sọ

      18. Ẹ̀kọ́ wo la rí kọ́ nínú ìwà Hábákúkù, gẹ́gẹ́ bí Hábákúkù 2:1 ti fi hàn?

      18 Wàyí o, Hábákúkù ń retí láti gbọ́ ohun tí Jèhófà tún fẹ́ bá a sọ. Wòlíì náà fi tìpinnu-tìpinnu sọ pé: “Ibi ìṣọ́ mi ni èmi yóò dúró sí, èmi yóò sì mú ìdúró mi lórí odi ààbò; èmi yóò sì máa ṣọ́ ẹ̀ṣọ́, láti rí ohun tí yóò sọ nípasẹ̀ mi, àti ohun tí èmi yóò fi fèsì nígbà tí a bá fi ìbáwí tọ́ mi sọ́nà.” (Hábákúkù 2:1) Pẹ̀lú ìháragàgà ni Hábákúkù fẹ́ mọ ohun tí Ọlọ́run yóò tún gba ẹnu rẹ̀ sọ gẹ́gẹ́ bíi wòlíì. Ìgbàgbọ́ tó ní nínú Jèhófà pé, ó jẹ́ Ọlọ́run tí kì í fàyè gba ohun burúkú, mú kó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe kàyéfì nípa ìdí tí ìwà ibi fi ń gbilẹ̀ sí i, àmọ́ ṣá o, ó ṣe tán láti jẹ́ kí èrò ọkàn òun yí padà. Tóò, àwa náà ńkọ́? Báa bá tiẹ̀ ń ṣe kàyéfì nípa ìdí tí Jèhófà fi fàyè gba àwọn nǹkan kan tí kò dára, ìgbẹ́kẹ̀lé táa ní pé ó jẹ́ Ọlọ́run òdodo yẹ kó ràn wá lọ́wọ́ láti máa bá ìdúróṣinṣin wa nìṣó, ká sì dúró dè é.—Sáàmù 42: 5, 11.

  • Jèhófà Kò Ní Fi Nǹkan Falẹ̀
    Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
    • 1. Ìpinnu wo làwọn èèyàn Jèhófà ti ṣe, kí sì ni èyí ti sún wọn láti ṣe?

      “IBI ìṣọ́ mi ni èmi yóò dúró sí.” Ìpinnu tí Hábákúkù, wòlíì Ọlọ́run ṣe nìyẹn. (Hábákúkù 2:1) Àwọn èèyàn Jèhófà ní ọ̀rúndún yìí ti ṣe irú ìpinnu kan náà. Látàrí èyí, wọ́n ti fi tìtaratìtara dáhùn sí ìpè tó dún nígbà àpéjọpọ̀ àgbègbè mánigbàgbé táa ṣe ní September 1922, pé: “Ọjọ́ ńlá lọjọ́ yìí o. Ẹ wò ó, Ọba náà ti jẹ! Ẹ̀yin ni agbẹnusọ tí ó jẹ́ aṣojú rẹ̀. Nítorí náà, ẹ fọn rere, ẹ fọn rere, ẹ fọn rere, Ọba náà àti ìjọba rẹ̀.”

      2. Nígbà táa dá àwọn ẹni àmì òróró padà sẹ́nu iṣẹ́ pẹrẹu lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kìíní, kí ni wọ́n polongo?

      2 Lẹ́yìn Ogun Àgbáyé Kìíní, Jèhófà mú àwọn àṣẹ́kù ẹni àmì òróró rẹ̀ padà sẹ́nu iṣẹ́ ní pẹrẹu. Gẹ́gẹ́ bíi ti Hábákúkù, olúkúlùkù wọn lè polongo pé: “Ibi ìṣọ́ mi ni èmi yóò dúró sí, èmi yóò sì mú ìdúró mi lórí odi ààbò; èmi yóò sì máa ṣọ́ ẹ̀ṣọ́, láti rí ohun tí yóò sọ nípasẹ̀ mi.” A lo àwọn ọ̀rọ̀ Hébérù náà fún “ìṣọ́” àti “ẹ̀ṣọ́” léraléra nínú ọ̀pọ̀ àsọtẹ́lẹ̀.

      “Kì Yóò Pẹ́”

      3. Èé ṣe táa fi gbọ́dọ̀ máa báa nìṣó ní ṣíṣọ́nà?

      3 Báwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti ń polongo ìkìlọ̀ Ọlọ́run lónìí, wọ́n gbọ́dọ̀ wà lójúfò nígbà gbogbo láti máa kọbi ara sí àwọn ọ̀rọ̀ àsọparí tí Jésù sọ nínú àsọtẹ́lẹ̀ pàtàkì náà pé: “Ẹ máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà, nítorí ẹ kò mọ ìgbà tí ọ̀gá ilé náà ń bọ̀, yálà nígbà tí alẹ́ ti lẹ́ tàbí ní ọ̀gànjọ́ òru tàbí ìgbà kíkọ àkùkọ tàbí ní kùtùkùtù òwúrọ̀; kí ó bàa lè jẹ́ pé, nígbà tí ó bá dé lójijì, òun kò ní bá yín lójú oorun. Ṣùgbọ́n ohun tí mo sọ fún yín ni mo sọ fún gbogbo ènìyàn, Ẹ máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà.” (Máàkù 13:35-37) Gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Hábákúkù, àti ti Jésù, a gbọ́dọ̀ máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà!

      4. Báwo ni ipò tiwa lónìí ṣe bá ti Hábákúkù mu ní nǹkan bí ọdún 628 ṣááju Sànmánì Tiwa?

      4 Ó ṣeé ṣe kí Hábákúkù ti kọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ ní nǹkan bí ọdún 628 ṣááju Sànmánì Tiwa, àní kí Bábílónì tó di agbára ayé pàápàá. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni wọ́n ti fi polongo pé ìdájọ́ Jèhófà ń bọ̀ wá sórí Jerúsálẹ́mù apẹ̀yìndà. Síbẹ̀, wọn ò lè sọ àkókò pàtó tí ìdájọ́ yẹn yóò dé. Ta ló mọ̀ pé ọdún mọ́kànlélógún péré ló kù tí yóò dé, àti pé Bábílónì ni Jèhófà yóò lò láti mú ìdájọ́ rẹ̀ ṣẹ? Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lónìí, a kò mọ ‘ọjọ́ àti wákàtí náà’ tí ètò yìí yóò lọ sópin, àmọ́, Jésù kìlọ̀ fún wa pé: “Ẹ wà ní ìmúratán, nítorí pé ní wákàtí tí ẹ kò ronú pé yóò jẹ́, ni Ọmọ ènìyàn ń bọ̀.”—Mátíù 24: 36, 44.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́