ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Kíkún Fún Ìdùnnú Nínú Ọlọ́run Ìgbàlà Wa
    Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
    • 18. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Hábákúkù ń retí ìṣòro, irú ẹ̀mí wo ló ní?

      18 Ogun sábà máa ń fa ìṣòro, àní fáwọn tó bá ṣẹ́gun lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn pàápàá. Ọ̀wọ́n gógó oúnjẹ lè wà. A lè pàdánù dúkìá. Sànmánì lè lọ́ tín-ín-rín. Bí ìyẹn bá ṣẹlẹ̀ sí wa, kí la máa ṣe? Hábákúkù ní ìwà táa lè fara wé, nítorí ó wí pé: “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igi ọ̀pọ̀tọ́ lè má yọ ìtànná, àjàrà sì lè má mú èso jáde; iṣẹ́ igi ólífì lè yọrí sí ìkùnà ní ti tòótọ́, àwọn ilẹ̀ onípele títẹ́jú sì lè má mú oúnjẹ wá ní ti tòótọ́; a lè ya agbo ẹran nípa kúrò nínú ọgbà ẹran ní ti tòótọ́, ọ̀wọ́ ẹran sì lè má sí nínú àwọn gbàgede; Síbẹ̀, ní tèmi, dájúdájú, èmi yóò máa yọ ayọ̀ ńláǹlà nínú Jèhófà; èmi yóò kún fún ìdùnnú nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.” (Hábákúkù 3:17, 18) Lọ́nà tó bọ́gbọ́n mu, Hábákúkù ń retí ìṣòro, kódà ó ń retí ìyàn pàápàá. Síbẹ̀, kò sígbà kan tí kò ní ìdùnnú nínú Jèhófà, ọ̀dọ̀ ẹni tí ìgbàlà rẹ̀ ti wá.

  • Kíkún Fún Ìdùnnú Nínú Ọlọ́run Ìgbàlà Wa
    Ilé Ìṣọ́—2000 | February 1
    • 20. Bí ìṣòro ìgbà díẹ̀ bá tilẹ̀ wà, kí ló yẹ ká pinnu láti ṣe?

      20 Ìṣòro ìgbà díẹ̀ yòówù táa bá dojú kọ, ẹ máà jẹ́ ká sọ ìgbàgbọ́ nù nínú agbára Jèhófà tí ń gbani là. Ọ̀pọ̀ nínú àwọn arákùnrin àti arábìnrin wa ní Áfíríkà, ní Ìlà Oòrùn Yúróòpù, àti ní àwọn ibòmíràn dojú kọ àwọn ìṣòro tó lékenkà, àmọ́, wọ́n ń báa nìṣó láti máa ‘yọ ayọ̀ ńlá nínú Jèhófà.’ Gẹ́gẹ́ bí tiwọn, ẹ má ṣe jẹ́ kí àwa náà jáwọ́ nínú ṣíṣe ohun kan náà tí wọ́n ń ṣe. Ẹ jẹ́ ká rántí pé, Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ ní Orísun “ìmí” wa. (Hábákúkù 3:19) Kò ní já wa kulẹ̀ láé. Ó dájú pé Amágẹ́dónì yóò dé, ó sì dájú pé ayé tuntun tí Ọlọ́run ṣèlérí yóò tẹ̀ lé e. (2 Pétérù 3:13) Nígbà náà ni “ilẹ̀ ayé yóò kún fún mímọ ògo Jèhófà bí omi ti bo òkun.” (Hábákúkù 2:14) Títí di àkókò àgbàyanu yẹn, ẹ jẹ́ ká tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Hábákúkù. Ní gbogbo ìgbà, ẹ jẹ́ ká máa ‘yọ ayọ̀ ńláǹlà nínú Jèhófà, ká sì máa kún fún ìdùnnú nínú Ọlọ́run ìgbàlà wa.’

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́