-
Ọjọ́ Ìdájọ́ Jèhófà Ti Sún Mọ́lé!Ilé Ìṣọ́—2001 | February 15
-
-
11. Kí ni kókó tó wà nínú Sefanáyà 1:8-11?
11 Sefanáyà 1:8-11 tún sọ nípa ọjọ́ Jèhófà pé: “‘Yóò sì ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ ẹbọ Jèhófà pé èmi yóò fún àwọn ọmọ aládé ní àfiyèsí dájúdájú, èmi yóò sì fún àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn tí ń wọ aṣọ ilẹ̀ òkèèrè ní àfiyèsí. Dájúdájú, èmi yóò sì fún olúkúlùkù ẹni tí ń gun pèpéle ní àfiyèsí ní ọjọ́ yẹn, àwọn tí ń fi ìwà ipá àti ẹ̀tàn kún ilé ọ̀gá wọn. Yóò sì ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ yẹn,’ ni àsọjáde Jèhófà, ‘ìró igbe ẹkún yóò ti Ẹnubodè Ẹja wá, àti híhu láti ìhà kejì, àti ìfọ́yángá ńláǹlà láti àwọn òkè kéékèèké. Ẹ hu, ẹ̀yin olùgbé Mákítẹ́ṣì, nítorí gbogbo àwọn ènìyàn tí ó jẹ́ oníṣòwò ni a ti pa lẹ́nu mọ́; gbogbo àwọn tí ń wọn fàdákà ni a ti ké kúrò.’”
-
-
Ọjọ́ Ìdájọ́ Jèhófà Ti Sún Mọ́lé!Ilé Ìṣọ́—2001 | February 15
-
-
13. Ní ìbámu pẹ̀lú àsọtẹ́lẹ̀ Sefanáyà, kí ni yóò ṣẹlẹ̀ nígbà táwọn ará Bábílónì bá gbéjà ko Jerúsálẹ́mù?
13 “Ọjọ́ yẹn” tí Júdà yóò jíhìn bá ọjọ́ tí Jèhófà yóò ṣèdájọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀ mu, tí yóò fòpin sí ìwà burúkú, tí yóò sì fi hàn pé òun ló ga lọ́lá jù lọ. Bí àwọn ará Bábílónì bá ṣe gbógun ti Jerúsálẹ́mù ni ìró igbe yóò wá láti Ẹnubodè Ẹja. Bóyá nítorí pé ibẹ̀ sún mọ́ ọjà tí wọ́n ti ń ta ẹja ni wọ́n fi ń pè é bẹ́ẹ̀. (Nehemáyà 13:16) Ogunlọ́gọ̀ àwọn ará Bábílónì yóò rọ́ wọ apá ibi tí wọ́n ń pè ní ìhà kejì, bákan náà, ‘ìfọ́yángá láti àwọn òkè kéékèèké’ lè dúró fún ìró àwọn ará Kálídíà tí ń rọ́ bọ̀. Híhu làwọn olùgbé Mákítẹ́ṣì, tó ṣeé ṣe kó jẹ́ apá òkè Àfonífojì Tírópóónì, yóò “hu.” Kí ni yóò mú kí wọ́n hu? Nítorí àwọn èèyàn ò ní ṣòwò níbẹ̀ mọ́, “àwọn tí ń wọn fàdákà” níbẹ̀ pàápàá á kógbá sílé.
-