-
Ẹ Jẹ́ Kí Gbogbo Wa Yin Jèhófà Lógo!Ilé Ìṣọ́—1997 | January 1
-
-
19. Báwo ni a ṣe lè nípìn-ín nínú ìmúṣẹ Hágáì 2:6, 7?
19 Ó jẹ́ ìdùnnú wa láti nípìn-ín nínú ìmúṣẹ òde òní ti Hágáì 2:6, 7 pé: ‘Báyìí ni Jèhófà àwọn ọmọ ogun wí, pé, Ẹ̀rìnkan ṣá, nígbà díẹ̀ sí i, ni èmi óò mi àwọn ọ̀run, àti ayé, àti òkun, àti ìyàngbẹ ilẹ̀. Èmi óò sì mi gbogbo orílẹ̀-èdè, àwọn ohun fífani lọ́kàn mọ́ra ti gbogbo orílẹ̀-èdè, yóò sì dé: èmi óò sì fi ògo kún ilé yìí, ni Jèhófà àwọn ọmọ ogun wí.’ Ìwọra, ìwà ìbàjẹ́, àti ìkórìíra ń gbalé gbòde jákèjádò ayé ní ọ̀rúndún ogún yìí. Ó ti wà nínú àwọn ọjọ́ ìkẹyìn rẹ̀ ní tòótọ́, Jèhófà sì ti bẹ̀rẹ̀ sí “mì” í, nípa mímú kí Àwọn Ẹlẹ́rìí rẹ̀ ‘kéde ọjọ́ ẹ̀san rẹ̀.’ (Aísáyà 61:2) Mímì àkọ́kọ́ yìí yóò dé òtéńté rẹ̀ nígbà tí ìparun ayé náà bá ṣẹlẹ̀ ní Amágẹ́dọ́nì, ṣùgbọ́n ṣáájú ìgbà náà, Jèhófà ń kó “àwọn ohun fífani lọ́kàn mọ́ra ti gbogbo orílẹ̀-èdè” jọ fún iṣẹ́ ìsìn rẹ̀—àwọn ọlọ́kàn tútù, àwọn ẹni bí àgùntàn tí wọ́n ń bẹ ní ilẹ̀ ayé. (Jòhánù 6:44) Nísinsìnyí, “ogunlọ́gọ̀ ńlá” yìí “ń ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́ ọlọ́wọ̀” nínú àgbàlá ilé ìjọsìn rẹ̀ ti ilẹ̀ ayé.—Ìṣípayá 7:9, 15.
-
-
Ògo Tí Ó Pọ̀ Ju Ti Ìṣáájú Lọ Tí Ilé Jèhófà NíIlé Ìṣọ́—1997 | January 1
-
-
Ògo Tí Ó Pọ̀ Ju Ti Ìṣáájú Lọ Tí Ilé Jèhófà Ní
“Èmi óò sì fi ògo kún ilé yìí, ni [Jèhófà, NW] àwọn ọmọ ogun wí.”—HÁGÁÌ 2:7.
1. Kí ni ìsopọ̀ tí ó wà láàárín ẹ̀mí mímọ́, ìgbàgbọ́ àti iṣẹ́?
NÍGBÀ tí ó ń wàásù láti ilé dé ilé, ọ̀kan lára Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà pàdé obìnrin kan tí ó jẹ́ ẹlẹ́sìn Pentecostal, ẹni tí ó wí pé, ‘Àwa ni a ní ẹ̀mí mímọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni ẹ ń ṣe iṣẹ́ náà.’ Lọ́nà ọgbọ́n, ó ṣàlàyé fún un pé, bí ẹnì kan bá ní ẹ̀mí mímọ́, kò sí àní-àní pé, a óò sún un láti ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run. Jákọ́bù 2:17 sọ pé: “Ìgbàgbọ́, bí kò bá ní àwọn iṣẹ́, jẹ́ òkú nínú ara rẹ̀.” Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ ẹ̀mí Jèhófà, Àwọn Ẹlẹ́rìí rẹ̀ ti mú ìgbàgbọ́ lílágbára dàgbà, ó sì ti fi ‘ògo kún ilé rẹ̀’ nípa gbígbé wọn kalẹ̀ láti ṣe iṣẹ́ òdodo—ní pàtàkì ‘wíwàásù ìhìn rere Ìjọba ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí a ń gbé gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí fún gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.’ Nígbà tí a bá ṣe iṣẹ́ yìí dé ibi tí ó tẹ́ Jèhófà lọ́rùn, “nígbà náà ni òpin yóò . . . dé.”—Mátíù 24:14.
-