-
Ẹ Jẹ́ Kí Ìfẹ́ Ará Tí Ẹ̀yin Ní Máa Bá A Lọ!Ilé Ìṣọ́—1997 | August 1
-
-
5. Báwo ni a ṣe mọ̀ pé Jèhófà máa ń fi ìmọ̀lára hàn fúnni?
5 Jèhófà ha máa ń fi irú ìmọ̀lára bẹ́ẹ̀ hàn fúnni bí? Bẹ́ẹ̀ ni. Fún àpẹẹrẹ, a kà nípa ìyà tí ó jẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ Ísírẹ́lì pé: “Nínú gbogbo wàhálà wọn, ó jẹ́ wàhálà fún un.” (Aísáyà 63:9, NW) Kì í ṣe pé Jèhófà rí wàhálà wọn nìkan ni; àánú wọn tún ṣe é. Ọ̀rọ̀ Jèhófà fúnra rẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ̀, tí a kọ sílẹ̀ nínú Sekaráyà 2:8 (NW) ṣàkàwé bí ìmọ̀lára rẹ̀ ti jinlẹ̀ tó: “Ẹni tí ó bá fọwọ́ kàn yín ń fọwọ́ kan ẹyinjú mi.”a Alálàyé kan sọ̀rọ̀ lórí ẹsẹ yìí pé: “Ojú jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà ara tí ó díjú jù lọ, tí ó sì tún jẹ́ ẹlẹgẹ́ jù lọ nínú ara ẹ̀dá ènìyàn; ẹyinjú—ibi tí ìmọ́lẹ̀ ń gbà wọnú ojú kí a baà lè ríran—ni ibi tí ó tètè ń nímọ̀lára jù lọ, tí ó sì tún ṣe pàtàkì jù lọ, nínú gbogbo ojú. Kò sí ọ̀rọ̀ míràn tí ó ju èyí lọ tí ó tún lè gbé èrò ìtọ́jú oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ jíjinlẹ̀ jù lọ yọ nípa ohun kan tí Jèhófà nífẹ̀ẹ́ sí.”
-
-
Ẹ Jẹ́ Kí Ìfẹ́ Ará Tí Ẹ̀yin Ní Máa Bá A Lọ!Ilé Ìṣọ́—1997 | August 1
-
-
a Àwọn olùtúmọ̀ kan sọ níhìn-ín pé kì í ṣe ojú Ọlọ́run ni ẹni tí ó bá fọwọ́ kan àwọn ènìyàn Ọlọ́run ń fọwọ́ kan, bí kò ṣe ojú Ísírẹ́lì tàbí ojú tirẹ̀ fúnra rẹ̀ pàápàá. Àṣìṣe yìí wá láti ọwọ́ àwọn akọ̀wé ìgbà Sànmánì Agbedeméjì, tí wọ́n yí ẹsẹ yìí pa dà nínú ìsapá òdì wọn láti ṣàtúnṣe àwọn ẹsẹ tí wọ́n rò pé kò fi ọ̀wọ̀ hàn. Nípa báyìí, wọn kò jẹ́ kí aráyé mọ bí ìfọ̀rọ̀rora-ẹni-wò tí Jèhófà ní ṣe jinlẹ̀ tó.
-