-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 15
-
-
Bí jàm̀bá kan bá ṣe gbòǹgbò náà, ìyókù igi náà yóò mọ̀ ọ́n lára. (Fiwé Matteu 3:10; 13:6.) Lọ́nà kan náà, Malaki kọ̀wé pé: “Ọjọ́ náà tí ń bọ̀ yóò sì jó wọn run, ni Oluwa awọn ọmọ-ogun wí, tí kì yóò fi ku gbòǹgbò tàbí ẹ̀ka fún wọn.” (Malaki 4:1) Ìtumọ̀ náà ṣe kedere—ìkékúrò pátápátá. Àwọn òbí (àwọn gbòǹgbò) ni a óò ké kúrò, àti àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú (àwọn ẹ̀ka).a Èyí tẹnumọ́ ẹrù-iṣẹ́ bàǹtà banta tí àwọn òbí ní lórí àwọn ọmọ wọn aláìtójúúbọ́; ọjọ́ ọ̀la wíwàpẹ́títí àwọn ọmọdé aláìtójúúbọ́ ni a lè pinnu nípasẹ̀ ìdúró àwọn òbí wọn níwájú Ọlọrun.—1 Korinti 7:14.
Èdè-ọ̀rọ̀ tí a lò ní Isaiah 37:31 àti Malaki 4:1 jẹ́rìí sí òtítọ́ náà pé àwọn ẹ̀ka (àti èso tí ó wà lára àwọn ọwọ́ ẹ̀ka) gba ìwàláàyè wọn láti ọ̀dọ̀ gbòǹgbò. Èyí ni kọ́kọ́rọ́ náà sí lílóye bí Jesu ṣe jẹ́ “kùkùté Jesse” àti “gbòǹgbò Dafidi.”
-
-
Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn ÒǹkàwéIlé-Ìṣọ́nà—1994 | August 15
-
-
a Àkọlé ara ibojì àwọn ara Phoenicia ìgbàanì kan lo èdè-ọ̀rọ̀ kan náà. Ó sọ nípa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣí ibojì náà pé: “Wọn kì yóò ní gbòǹgbò nísàlẹ̀ tàbí èso lókè!”—Vetus Testamentum, April 1961.
-