-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
3, 4. (a) Kí ni Jésù sọ ní ọjọ́ mẹ́fà ṣáájú ìyípadà ológo náà? (b) Ṣàpèjúwe ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìyípadà ológo náà.
3 Ọjọ́ mẹ́fà ṣáájú ìyípadà ológo náà, Jésù sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé: “A ti yan Ọmọkùnrin ènìyàn tẹ́lẹ̀ láti wá nínú ògo Bàbá rẹ̀ pẹ̀lú àwọn áńgẹ́lì rẹ̀, nígbà náà ni òun yóò sì san èrè iṣẹ́ fún olúkúlùkù ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí rẹ̀.” A óò mú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ṣẹ ní “ìparí ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan.” Jésù sọ síwájú sí i pé: “Ní òótọ́ ni mo wí fún yín pé àwọn kan wà lára àwọn wọnnì tí wọ́n dúró níhìn-ín tí kì yóò tọ́ ikú wò rárá títí wọn yóò fi kọ́kọ́ rí Ọmọkùnrin ènìyàn tí ń bọ̀ nínú ìjọba rẹ̀.” (Mátíù 16:27, 28; 24:3; 25:31-34, 41; Dáníẹ́lì 12:4) Ìyípadà ológo náà wáyé láti mú àwọn ọ̀rọ̀ tí a sọ gbẹ̀yìn wọ̀nyí ṣẹ.
-
-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
5. Ipa wo ni ìyípadà ológo náà ní lórí àpọ́sítélì Pétérù?
5 Àpọ́sítélì Pétérù ti fi Jésù hàn ṣáájú gẹ́gẹ́ bíi “Kristi náà, Ọmọkùnrin Ọlọ́run alààyè.” (Mátíù 16:16) Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ látọ̀run fìdí ìfihàn náà múlẹ̀, ìran ìyípadà ológo Jésù sì jẹ́ ìfojúsọ́nà fún wíwáa Kristi nínú agbára àti ògo Ìjọba, láti ṣèdájọ́ aráyé nígbẹ̀yìngbẹ́yín. Ní èyí tí ó lé ní 30 ọdún lẹ́yìn ìyípadà ológo náà, Pétérù kọ̀wé pé: “Kì í ṣe nípa títẹ̀lé àwọn ìtàn èké àdọ́gbọ́nhùmọ̀ lọ́nà àrékendá ni àwa fi sọ yín di ojúlùmọ̀ agbára àti wíwàníhìn-ín Olúwa wa Jésù Kristi, ṣùgbọ́n ó jẹ́ nípa dídi ẹlẹ́rìí olùfojúrí ọlá ńlá rẹ̀. Nítorí òun gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Bàbá, nígbà tí ògo ọlọ́lá ńlá gbé àwọn ọ̀rọ̀ bí irú ìwọ̀nyí wá fún un pé: ‘Èyí ni ọmọkùnrin mi, olùfẹ́ mi ọ̀wọ́n, ẹni tí èmi tìkára mi ti fi ojú rere tẹ́wọ́ gbà.’ Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni àwa gbọ́ tí a gbé wá láti ọ̀run nígbà tí a wà pẹ̀lú rẹ̀ ní òkè ńlá mímọ́ náà.”—Pétérù Kejì 1:16-18; Pétérù Kíní 4:17.
-
-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
7. (a) Nígbà wo ni ìran ìyípadà ológo náà bẹ̀rẹ̀ sí í ní ìmúṣẹ? (b) Nígbà wo ni Jésù san èrè iṣẹ́ fún àwọn kan ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí wọn?
7 Láti ìbẹ̀rẹ̀ “ọjọ́ Olúwa” ní 1914, a ti mú ọ̀pọ̀ lára ìran tí Jòhánù rí ṣẹ. (Ìṣípayá 1:10) ‘Wíwá nínú ògo Bàbá rẹ̀’ tí Jésù yóò wá ńkọ́, gẹ́gẹ́ bí ìyípadà ológo náà ti fi hàn ṣáájú? Ìran yìí bẹ̀rẹ̀ sí í nímùúṣẹ nígbà ìbí Ìjọba ọ̀run ti Ọlọ́run ní 1914. Nígbà tí Jésù yọ bí ọjọ́ nínú ìran àgbáyé gẹ́gẹ́ bí Ọba tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ gorí ìtẹ́, ìyẹn jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ tuntun kan, kí a sọ ọ́ lọ́nà bẹ́ẹ̀. (Pétérù Kejì 1:19; Ìṣípayá 11:15; 22:16) Ní àkókò yẹn, Jésù ha san èrè iṣẹ́ fún àwọn kan ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni. Ẹ̀rí lílágbára wà pé àjíǹde àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró sí ọ̀run bẹ̀rẹ̀ kété lẹ́yìn ìgbà yẹn.—Tímótì Kejì 4:8; Ìṣípayá 14:13.
8. Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wo ní yóò sàmì sí òtéńté ìmúṣẹ ìran ìyípadà ológo náà?
8 Ṣùgbọ́n, láìpẹ́, Jésù yóò dé “nínú ògo rẹ̀, àti gbogbo àwọn áńgẹ́lì pẹ̀lú rẹ̀,” kí ó baà lè ṣèdájọ́ aráyé lápapọ̀. (Mátíù 25:31) Ní àkókò yẹn, yóò fara rẹ̀ hàn nínú gbogbo ògo ọlọ́lá ńlá rẹ̀, yóò sì san èrè iṣẹ́ tí ó tọ́ fún “olúkúlùkù” ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí rẹ̀. Àwọn ẹni bí àgùntàn yóò jogún ìyè àìnípẹ̀kun nínú Ìjọba tí a ti pèsè sílẹ̀ fún wọn, àwọn ẹni bí ewúrẹ́ yóò sì lọ sínú “ìkékúrò àìnípẹ̀kun.” Ẹ wo irú òpin kíkọyọyọ tí ìyẹn yóò jẹ́ sí ìmúṣẹ ìran ìyípadà ológo náà!—Mátíù 25:34, 41, 46; Máàkù 8:38; Tẹsalóníkà Kejì 1:6-10.
-
-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
12. Nínú àyíká ọ̀rọ̀ ìyípadà ológo náà, àwọn wo ni Mósè àti Èlíjà dúró fún?
12 Nígbà náà, àwọn wo ni Mósè àti Èlíjà dúró fún nínú àyíká ọ̀rọ̀ inú ìran ìyípadà ológo náà? Lúùkù sọ pé, wọ́n fara hàn pẹ̀lú Jésù “pẹ̀lú ògo.” (Lúùkù 9:31) Ní kedere, wọ́n dúró fún àwọn Kristẹni tí a ti fi ẹ̀mí mímọ́ yàn, gẹ́gẹ́ bí “ajùmọ̀jogún” pẹ̀lú Jésù, tí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ gba ìrètí àgbàyanu ti ṣíṣe wọ́n “lógo pa pọ̀” pẹ̀lú rẹ̀. (Róòmù 8:17) Àwọn ẹni àmì òróró tí a jí dìde yóò wà pẹ̀lú Jésù nígbà tí ó bá wá nínú ògo Bàbá rẹ̀ láti “san èrè iṣẹ́ fún olúkúlùkù ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí rẹ̀.”—Mátíù 16:27.
-