-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
3, 4. (a) Kí ni Jésù sọ ní ọjọ́ mẹ́fà ṣáájú ìyípadà ológo náà? (b) Ṣàpèjúwe ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìyípadà ológo náà.
3 Ọjọ́ mẹ́fà ṣáájú ìyípadà ológo náà, Jésù sọ fún àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé: “A ti yan Ọmọkùnrin ènìyàn tẹ́lẹ̀ láti wá nínú ògo Bàbá rẹ̀ pẹ̀lú àwọn áńgẹ́lì rẹ̀, nígbà náà ni òun yóò sì san èrè iṣẹ́ fún olúkúlùkù ní ìbámu pẹ̀lú ìhùwàsí rẹ̀.” A óò mú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ṣẹ ní “ìparí ètò ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan.” Jésù sọ síwájú sí i pé: “Ní òótọ́ ni mo wí fún yín pé àwọn kan wà lára àwọn wọnnì tí wọ́n dúró níhìn-ín tí kì yóò tọ́ ikú wò rárá títí wọn yóò fi kọ́kọ́ rí Ọmọkùnrin ènìyàn tí ń bọ̀ nínú ìjọba rẹ̀.” (Mátíù 16:27, 28; 24:3; 25:31-34, 41; Dáníẹ́lì 12:4) Ìyípadà ológo náà wáyé láti mú àwọn ọ̀rọ̀ tí a sọ gbẹ̀yìn wọ̀nyí ṣẹ.
-
-
Nígbà Tí Jésù Bá Wá Nínú Ògo ÌjọbaIlé Ìṣọ́—1997 | May 15
-
-
5. Ipa wo ni ìyípadà ológo náà ní lórí àpọ́sítélì Pétérù?
5 Àpọ́sítélì Pétérù ti fi Jésù hàn ṣáájú gẹ́gẹ́ bíi “Kristi náà, Ọmọkùnrin Ọlọ́run alààyè.” (Mátíù 16:16) Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ látọ̀run fìdí ìfihàn náà múlẹ̀, ìran ìyípadà ológo Jésù sì jẹ́ ìfojúsọ́nà fún wíwáa Kristi nínú agbára àti ògo Ìjọba, láti ṣèdájọ́ aráyé nígbẹ̀yìngbẹ́yín. Ní èyí tí ó lé ní 30 ọdún lẹ́yìn ìyípadà ológo náà, Pétérù kọ̀wé pé: “Kì í ṣe nípa títẹ̀lé àwọn ìtàn èké àdọ́gbọ́nhùmọ̀ lọ́nà àrékendá ni àwa fi sọ yín di ojúlùmọ̀ agbára àti wíwàníhìn-ín Olúwa wa Jésù Kristi, ṣùgbọ́n ó jẹ́ nípa dídi ẹlẹ́rìí olùfojúrí ọlá ńlá rẹ̀. Nítorí òun gba ọlá àti ògo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Bàbá, nígbà tí ògo ọlọ́lá ńlá gbé àwọn ọ̀rọ̀ bí irú ìwọ̀nyí wá fún un pé: ‘Èyí ni ọmọkùnrin mi, olùfẹ́ mi ọ̀wọ́n, ẹni tí èmi tìkára mi ti fi ojú rere tẹ́wọ́ gbà.’ Bẹ́ẹ̀ ni, àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni àwa gbọ́ tí a gbé wá láti ọ̀run nígbà tí a wà pẹ̀lú rẹ̀ ní òkè ńlá mímọ́ náà.”—Pétérù Kejì 1:16-18; Pétérù Kíní 4:17.
-