ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Bí Ẹ Bá Jẹ Owó-Orí, Ẹ San Owó-Orí”
    Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | November 15
    • Jẹ́ aláìlẹ́gàn. Àwọn Kristian alábòójútó gbọ́dọ̀ jẹ́ “aláìlẹ́gàn” kí wọ́n baà lè tóótun fún ipò wọn. Bákan náà, gbogbo ìjọ lódidi níláti jẹ́ aláìlẹ́gàn lójú Ọlọrun. (1 Timoteu 3:⁠2; fiwé Efesu 5:27.) Nítorí náà wọ́n ń làkàkà láti di ìfùsì rere mú nínú ẹgbẹ́ àwùjọ, kódà nígbà tí ó bá kan ti sísan owó-orí. Jesu Kristi fúnraarẹ̀ fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ lọ́nà yìí. A bi Peteru ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ léèrè bí Jesu bá san owó-orí tẹ́ḿpìlì, ọ̀ràn kékeré kan tí ó wémọ́ dírákímà méjì. Nítòótọ́, owó-orí yìí kò kan Jesu, níwọ̀n bí tẹ́ḿpìlì náà ti jẹ́ ilé Bàbá rẹ̀ tí kò sì sí ọba tí í gbé owó-orí ka ọmọkùnrin òun tìkáraarẹ̀ lórí. Ohun tí Jesu náà sọ nìyẹn; síbẹ̀ ó san owó-orí náà. Níti tòótọ́, ó tilẹ̀ lo iṣẹ́ ìyanu láti pèsè owó tí wọ́n nílò! Èéṣe tí òun fi san owó-orí tí ó lómìnira yíyẹ láti máṣe san? Gẹ́gẹ́ bí Jesu fúnraarẹ̀ ti sọ, ó jẹ́ “kí a má baà mú wọn kọsẹ̀.”​—⁠Matteu 17:​24-⁠27, NW.b

  • “Bí Ẹ Bá Jẹ Owó-Orí, Ẹ San Owó-Orí”
    Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | November 15
    • b Lọ́nà tí ó dùnmọ́ni, Matteu ni ìwé Ìhìnrere kanṣoṣo náà tí ó ṣe àkọsílẹ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ yìí nínú ìgbésí-ayé Jesu lórí ilẹ̀-ayé. Gẹ́gẹ́ bí agbowó-orí kan tẹ́lẹ̀rí, kò sí iyèméjì pé Matteu fúnraarẹ̀ ni ìṣarasíhùwà Jesu nínú ọ̀ràn yìí wú lórí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́