-
“Bí Ẹ Bá Jẹ Owó-Orí, Ẹ San Owó-Orí”Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | November 15
-
-
Jẹ́ aláìlẹ́gàn. Àwọn Kristian alábòójútó gbọ́dọ̀ jẹ́ “aláìlẹ́gàn” kí wọ́n baà lè tóótun fún ipò wọn. Bákan náà, gbogbo ìjọ lódidi níláti jẹ́ aláìlẹ́gàn lójú Ọlọrun. (1 Timoteu 3:2; fiwé Efesu 5:27.) Nítorí náà wọ́n ń làkàkà láti di ìfùsì rere mú nínú ẹgbẹ́ àwùjọ, kódà nígbà tí ó bá kan ti sísan owó-orí. Jesu Kristi fúnraarẹ̀ fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ lọ́nà yìí. A bi Peteru ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ léèrè bí Jesu bá san owó-orí tẹ́ḿpìlì, ọ̀ràn kékeré kan tí ó wémọ́ dírákímà méjì. Nítòótọ́, owó-orí yìí kò kan Jesu, níwọ̀n bí tẹ́ḿpìlì náà ti jẹ́ ilé Bàbá rẹ̀ tí kò sì sí ọba tí í gbé owó-orí ka ọmọkùnrin òun tìkáraarẹ̀ lórí. Ohun tí Jesu náà sọ nìyẹn; síbẹ̀ ó san owó-orí náà. Níti tòótọ́, ó tilẹ̀ lo iṣẹ́ ìyanu láti pèsè owó tí wọ́n nílò! Èéṣe tí òun fi san owó-orí tí ó lómìnira yíyẹ láti máṣe san? Gẹ́gẹ́ bí Jesu fúnraarẹ̀ ti sọ, ó jẹ́ “kí a má baà mú wọn kọsẹ̀.”—Matteu 17:24-27, NW.b
-
-
“Bí Ẹ Bá Jẹ Owó-Orí, Ẹ San Owó-Orí”Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | November 15
-
-
b Lọ́nà tí ó dùnmọ́ni, Matteu ni ìwé Ìhìnrere kanṣoṣo náà tí ó ṣe àkọsílẹ̀ ìṣẹ̀lẹ̀ yìí nínú ìgbésí-ayé Jesu lórí ilẹ̀-ayé. Gẹ́gẹ́ bí agbowó-orí kan tẹ́lẹ̀rí, kò sí iyèméjì pé Matteu fúnraarẹ̀ ni ìṣarasíhùwà Jesu nínú ọ̀ràn yìí wú lórí.
-