-
Báwo Ni Ìwọ Ṣe Ń Yanjú Aáwọ̀?Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | July 15
-
-
Yíyanjú Àwọn Aáwọ̀ Lílekoko
“Pẹ̀lúpẹ̀lù bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀ ọ́, lọ sọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ fún un ti ìwọ tirẹ̀ méjì: bí ó bá gbọ́ tìrẹ, ìwọ mú arákùnrin rẹ bọ̀sípò. Ṣùgbọ́n bí kò bá gbọ́ tìrẹ, nígbà náà ni kí ìwọ kí ó mú ẹnìkan tàbí méjì pẹ̀lú araarẹ, kí gbogbo ọ̀rọ̀ ní ẹnu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta baà le fi ìdí múlẹ̀. Bí ó bá sí kọ̀ láti gbọ́ wọn, wí fún ìjọ ènìyàn Ọlọrun: bí ó ba sì kọ̀ láti gbọ́ ti ìjọ ènìyàn Ọlọrun, jẹ́ kí ó dàbí kèfèrí sí ọ àti agbowóòde.”—Matteu 18:15-17.
Kí a sọ pé Ju kan (tàbí lẹ́yìn náà, Kristian kan) bá kówọnú àwọn ìṣòro lílekoko pẹ̀lú olùjọ́sìn Jehofa ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ ńkọ́? Ẹni náà tí ó ronú pé a ti ṣẹ òun ni ó yẹ kí ó gbé ìgbésẹ̀ àkọ́kọ́. Ó yẹ kí ó jíròrò àwọn ọ̀ràn pẹ̀lú ẹni tí ó ṣe láìfí síi ní ìdákọ́ńkọ́. Nípa ṣíṣàì gbìyànjú láti wá ìtìlẹ́yìn fún araarẹ̀ nínú ọ̀ràn náà, dájúdájú ó ṣeéṣe jùlọ pé kí ó jèrè arákùnrin rẹ̀ padà, pàápàá jùlọ bí ó bá jẹ́ pé kìkì èdèkòyedè kan tí a lè tètè yanjú kíákíá ni. Ohun gbogbo ni a óò yanjú lọ́nà tí ó túbọ̀ rọrùn bí ó bá jẹ́ pé àwọn wọnnì tí ọ̀ràn kàn ní tààràtà nìkan ni wọ́n mọ̀ nípa ọ̀ràn náà.
-
-
Báwo Ni Ìwọ Ṣe Ń Yanjú Aáwọ̀?Ilé-Ìṣọ́nà—1994 | July 15
-
-
Ṣíṣeéṣe náà pé kí a yọ oníwà-àìtọ́ kan tí kò ronúpìwàdà lẹ́gbẹ́ fihàn pé Matteu 18:15-17 kò níí ṣe pẹ̀lú àwọn aáwọ̀ tí kò tó nǹkan. Jesu ń tọ́kasí àwọn láìfí tí ó wúwo, síbẹ̀ tí ó jẹ́ irú èyí tí a lè yanjú láàárín àwọn ẹni méjì tí ọ̀ràn kan náà. Fún àpẹẹrẹ, láìfí náà lè jẹ́ ìfọ̀rọ̀ èké banijẹ́, tí ó nípa lórí ìfùsì ẹni náà lọ́nà lílekoko. Tàbí ó lè níí ṣe pẹ̀lú àwọn ọ̀ràn ìnáwó, nítorí pé àwọn ẹsẹ tí ó tẹ̀lé e ní àkàwé Jesu nípa ẹrú aláìláàánú tí a dárí gbèsè ńláǹlà jì nínú. (Matteu 18:23-35) Ẹ̀yáwó kan tí a kò san padà ní àkókò wulẹ̀ lè jẹ́ ìṣòro kan tí ó rọrùn láti gbójúfòdá tí a lè tètè yanjú láàárín àwọn ènìyàn méjì. Ṣùgbọ́n ó lè di ẹ̀ṣẹ̀ wíwúwo, ìyẹn ni, olè jíjà, bí ayáwó náà bá fi oríkunkun kọ̀ láti san gbèsè tí ó jẹ padà.
-