-
Àwọn Akọrin Tí A Tẹ̀ Lọ́dàá—Sísọ Ara Di Alábùkù Lórúkọ ÌsìnJí!—1996 | February 8
-
-
Origen—tí a mọ̀ dáadáa mọ Hexapla rẹ̀, àwọn ẹ̀dà Ìwé Mímọ́ Lédè Heberu tí a ṣètò sí òpó ìlà mẹ́fà—ni a bí ní nǹkan bí ọdún 185 Sànmánì Tiwa. Nígbà tí ó wà ní ọmọ ọdún 18, àwọn àwíyé rẹ̀ lórí ìsìn Kristian ti sọ ọ́ di olókìkí. Síbẹ̀, ó ń ṣàníyàn nípa pé kí a má ṣi òkìkí òun láàárín àwọn obìnrin túmọ̀. Nítorí náà, ní mímú àwọn ọ̀rọ̀ Jesu náà lólówuuru pé, “awọn ìwẹ̀fà sì wà tí wọ́n ti sọ ara wọn di ìwẹ̀fà nítìtorí ìjọba awọn ọ̀run,” ó tẹ ara rẹ̀ lọ́dàá. (Matteu 19:12)a Ìwà aláìdàgbàdénú, àláìronújinlẹ̀ ni ó jẹ́—èyí tí ó wá kábàámọ̀ gidigidi nígbà tí ó yá nínú ìgbésí ayé rẹ̀.
-
-
Àwọn Akọrin Tí A Tẹ̀ Lọ́dàá—Sísọ Ara Di Alábùkù Lórúkọ ÌsìnJí!—1996 | February 8
-
-
a Nípa ọ̀rọ̀ Jesu, àkíyèsí ẹsẹ̀ ìwé lórí Westminster Version of the Sacred Scriptures: The New Testament ti Roman Kátólíìkì ṣàlàyé pé: “Kì í ṣe nípa títẹ ara ìyára lọ́dàá, ṣùgbọ́n nípa ti ẹ̀mí nípa ète tàbí ẹ̀jẹ́.” Bákan náà, ìwé A Commentary on the New Testament, láti ọwọ́ John Trapp, sọ pé: “Kì í ṣe pé kí wọ́n tẹ ara wọn lọ́dàá, bí Origen àti àwọn kan ti ṣe ní ìgbà láéláé, nítorí ṣíṣi ẹsẹ yìí lóye . . . ṣùgbọ́n, kí wọ́n wà ní àpọ́n, kí wọ́n lè jọ́sìn Ọlọrun pẹ̀lú òmìnira tí ó túbọ̀ gbé pẹ́ẹ́lí sí i.”
-