-
Ǹjẹ́ O Mọ̀?Ilé Ìṣọ́—2011 | October 1
-
-
▪ Nígbà tó kù díẹ̀ kí Jésù kú, ó sọ̀rọ̀ nípa ìwà ìrẹ́jẹ tó bùáyà tó ń ṣẹlẹ̀ nínú tẹ́ńpìlì. Bíbélì ròyìn pé: “Jésù . . . lé gbogbo àwọn tí ń tà, tí wọ́n sì ń rà nínú tẹ́ńpìlì síta, ó sì sojú tábìlì àwọn olùpààrọ̀ owó dé àti bẹ́ǹṣì àwọn tí ń ta àdàbà. Ó sì wí fún wọn pé: “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ilé mi ni a óò máa pè ní ilé àdúrà,’ ṣùgbọ́n ẹ ń sọ ọ́ di hòrò àwọn ọlọ́ṣà.’”—Mátíù 21:12, 13.
-
-
Ǹjẹ́ O Mọ̀?Ilé Ìṣọ́—2011 | October 1
-
-
Bí Jésù ṣe bá àwọn tó ń pààrọ̀ owó wí pé wọ́n ti sọ tẹ́ńpìlì di “hòrò àwọn ọlọ́ṣà” fi hàn kedere pé iye tí wọ́n ń gbà lọ́wọ́ àwọn tó fẹ́ pààrọ̀ owó ti pọ̀ jù.
-