ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Àpèjúwe Méjì Nípa Ọgbà Àjàrà
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
    • Jésù tún sọ àpèjúwe míì lẹ́yìn ìyẹn. Lọ́tẹ̀ yìí, Jésù fi hàn pé ohun táwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn ṣe kọjá pé wọn ò sin Ọlọ́run. Ìkà burúkú ni wọ́n. Jésù sọ pé: “Ọkùnrin kan gbin àjàrà, ó sì ṣe ọgbà yí i ká, ó gbẹ́ ẹkù sí ibi tí wọ́n ti ń fún wáìnì, ó sì kọ́ ilé gogoro kan; ó wá gbé e fún àwọn tó ń dáko, ó sì rin ìrìn àjò lọ sí ilẹ̀ òkèèrè. Nígbà tí àsìkò tó, ó rán ẹrú kan lọ sọ́dọ̀ àwọn tó ń dáko náà pé kó gbà lára àwọn èso ọgbà àjàrà náà lọ́wọ́ wọn. Àmọ́ wọ́n mú un, wọ́n lù ú, wọ́n sì ní kó máa lọ lọ́wọ́ òfo. Ó tún rán ẹrú míì sí wọn àmọ́ wọ́n lù ú ní orí, wọ́n sì kàn án lábùkù. Ó rán ẹlòmíì, wọ́n sì pa á, ó tún rán ọ̀pọ̀ àwọn míì, wọ́n lu àwọn kan nínú wọn, wọ́n sì pa àwọn míì.”—Máàkù 12:1-5.

      Ṣé àpèjúwe yìí máa yé àwọn èèyàn? Ó ṣeé ṣe kí wọ́n rántí ohun tí wòlíì Àìsáyà sọ nígbà tó ń dẹ́bi fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé: “Ilé Ísírẹ́lì ni ọgbà àjàrà Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun; àwọn èèyàn Júdà sì ni oko tó fẹ́ràn. Ó ń retí ìdájọ́ òdodo, àmọ́ wò ó! ìrẹ́jẹ ló wà.” (Àìsáyà 5:7) Ohun tí Àìsáyà sọ yìí jọra pẹ̀lú àpèjúwe Jésù yẹn. Jèhófà ló gbin àjàrà, orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì ló dà bí ọgbà àjàrà náà, Òfin Ọlọ́run ló dà bí ọgbà tó yí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ká, tó sì ń dáàbò bò wọ́n. Jèhófà rán àwọn wòlíì sí wọn láti tọ́ wọn sọ́nà, kí wọ́n lè máa so èso tó dáa.

  • Àpèjúwe Méjì Nípa Ọgbà Àjàrà
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
    • Láìmọ̀, ṣe ni wọ́n ń dá ara wọn lẹ́jọ́, torí wọ́n wà lára “àwọn tó ń dáko” tí Jèhófà ní kó máa bójú tó orílẹ̀-èdè Ísírẹ́lì tó jẹ́ “ọgbà àjàrà” rẹ̀. Ọ̀kan lára èso tí Jèhófà ń retí látọ̀dọ̀ wọn ni pé kí wọ́n nígbàgbọ́ nínú Ọmọ rẹ̀, ìyẹn Mèsáyà. Jésù wá kọjú sáwọn aṣáájú ẹ̀sìn yẹn, ó sì sọ fún wọn pé: “Ṣé ẹ ò ka ìwé mímọ́ yìí rí ni, pé: ‘Òkúta tí àwọn kọ́lékọ́lé kọ̀ sílẹ̀, òun ló wá di olórí òkúta igun ilé. Ọ̀dọ̀ Jèhófà ni èyí ti wá, ó sì jẹ́ ìyanu lójú wa’?” (Máàkù 12:10, 11) Lẹ́yìn náà, Jésù ṣàlàyé fún wọn pé: “Ìdí nìyí tí mo fi sọ fún yín pé, a máa gba Ìjọba Ọlọ́run kúrò lọ́wọ́ yín, a sì máa fún orílẹ̀-èdè tó ń mú èso rẹ̀ jáde.”—Mátíù 21:43.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́