-
Ẹ̀kọ́ Tí Àpèjúwe Wúńdíá Mẹ́wàá Kọ́ WaJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Jésù ti ń dáhùn ìbéèrè táwọn àpọ́sítélì ẹ̀ bi í nípa àmì tó máa fi hàn pé ó ti wà níhìn-ín àti àmì ìparí ètò àwọn nǹkan. Orí ọ̀rọ̀ yẹn náà ni wọ́n ṣì wà, ó wá sọ àpèjúwe míì fún wọn láti gbà wọ́n níyànjú. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó bá wà láyé nígbà tí Jésù bá wà níhìn-ín ló máa rí bí àsọtẹ́lẹ̀ yẹn ṣe ń ṣẹ.
Ó bẹ̀rẹ̀ àpèjúwe náà báyìí, ó ní: “A lè fi Ìjọba ọ̀run wé wúńdíá mẹ́wàá tí wọ́n mú fìtílà wọn, tí wọ́n sì jáde lọ pàdé ọkọ ìyàwó. Márùn-ún nínú wọ́n jẹ́ òmùgọ̀, márùn-ún sì jẹ́ olóye.”—Mátíù 25:1, 2.
Kì í ṣe ohun tí Jésù ń sọ ni pé ìdajì nínú àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó máa jogún Ìjọba ọ̀run á ya òmùgọ̀, tí ìdajì tó kù á wá jẹ́ olóye. Àmọ́ ohun tó ń sọ ni pé ọmọ ẹ̀yìn kọ̀ọ̀kan tó bá máa jogún Ìjọba náà máa ní láti pinnu bóyá òun máa wà lójúfò, àbí òun máa jẹ́ kí nǹkan míì gba òun lọ́kàn. Síbẹ̀, ọkàn Jésù balẹ̀ pé àwọn ìránṣẹ́ òun máa jẹ́ olóòótọ́ délẹ̀, Baba òun á sì bù kún wọn.
Nínú àpèjúwe yẹn, àwọn wúńdíá mẹ́wẹ̀ẹ̀wá máa lọ pàdé ọkọ ìyàwó náà, kí wọ́n lè kí i káàbọ̀, kí wọ́n sì jọ máa bá ètò ìgbéyàwó lọ. Tí ọkọ ìyàwó náà bá dé, àwọn wúńdíá yẹn máa tan fìtílà wọn kí ojú ọ̀nà lè mọ́lẹ̀, kí wọ́n sì yẹ́ ọkọ ìyàwó sí bó ṣe ń mú ìyàwó rẹ̀ lọ sí yàrá tó ti ṣètò. Àmọ́ kí ló wá ṣẹlẹ̀?
-
-
Ẹ̀kọ́ Tí Àpèjúwe Wúńdíá Mẹ́wàá Kọ́ WaJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Ó yé àwọn àpọ́sítélì pé Jésù ni ọkọ ìyàwó inú àpèjúwe yẹn dúró fún, torí ó tiẹ̀ ti fi ara ẹ̀ wé ọkọ ìyàwó tẹ́lẹ̀. (Lúùkù 5:34, 35) Àwọn wo wá ni àwọn wúńdíá tó jẹ́ olóye yẹn? Nígbà tí Jésù ń sọ̀rọ̀ nípa “agbo kékeré” tó máa jogún Ìjọba náà, ó sọ pé: “Ẹ múra, kí ẹ sì wà ní sẹpẹ́, kí ẹ jẹ́ kí àwọn fìtílà yín máa jó.” (Lúùkù 12:32, 35) Torí náà, ó yé àwọn àpọ́sítélì pé àwọn ló dúró fún àwọn wúńdíá tí Jésù ń sọ yẹn. Àmọ́ ẹ̀kọ́ wo ni Jésù fẹ́ fi àpèjúwe yìí kọ́ wọn?
-