-
Jòhánù Arinibọmi Ṣètò Ọ̀nà Sílẹ̀Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Ìrísí Jòhánù àti ọ̀rọ̀ ẹnu ẹ̀ wúni lórí gan-an. Irun ràkúnmí ni wọ́n fi ṣe aṣọ tó ń wọ̀, ó sì máa ń de bẹ́líìtì tí wọ́n fi awọ ṣe. Oríṣi tata kan tí wọ́n ń pè ní eésú àti oyin ìgàn ló máa ń jẹ. Ohun tó ń wàásù fáwọn èèyàn ni pé: “Ẹ ronú pìwà dà, torí Ìjọba ọ̀run ti sún mọ́lé.”—Mátíù 3:2.
Ọ̀rọ̀ Jòhánù máa ń wú àwọn tó ń fetí sí i lórí. Ọ̀pọ̀ nínú wọn sì rí i pé ó yẹ káwọn ronú pìwà dà, ìyẹn ni pé, kí wọ́n yí ìwà àti ìṣe wọn pa dà, kí wọ́n sì yẹra fáwọn ohun tí ò dáa tí wọ́n ń ṣe tẹ́lẹ̀. “Jerúsálẹ́mù àti gbogbo Jùdíà àti gbogbo ìgbèríko tó yí Jọ́dánì ká” làwọn èèyàn ti ń wá sọ́dọ̀ rẹ̀. (Mátíù 3:5) Ọ̀pọ̀ àwọn tó wá bá Jòhánù ló ronú pìwà dà. Jòhánù á wá rì wọ́n bọmi nínú Odò Jọ́dánì. Kí nìdí tó fi ń ṣe bẹ́ẹ̀?
-
-
Jòhánù Arinibọmi Ṣètò Ọ̀nà Sílẹ̀Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Torí náà, ó ṣe kedere pé bí Jòhánù ṣe ń kéde fáwọn èèyàn pé kí wọ́n “ronú pìwà dà, torí Ìjọba ọ̀run ti sún mọ́lé” bọ́ sákòókò gan-an. (Mátíù 3:2) Ṣe ló ń jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ̀ pé Jésù Kristi, Ọba tí Jèhófà yàn, máa tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀.
-