-
Ṣé Ẹní Bá Ń Ṣàníyàn Ò Nígbàgbọ́ Ni?Jí!—2004 | June 8
-
-
Ojú Ìwòye Bíbélì
Ṣé Ẹní Bá Ń Ṣàníyàn Ò Nígbàgbọ́ Ni?
“A FÒFIN DE ṢÍṢÀNÍYÀN.” Lábẹ́ àkọlé yìí, pásítọ̀ kan tó gbáyé lápá ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rúndún ogún kọ̀wé pé kì í ṣe pé kéèyàn máa ṣàníyàn nípa àwọn nǹkan tara burú nìkan ni àmọ́, “ẹ̀ṣẹ̀ wíwúwo gan-an ló jẹ́.” Lẹ́nu àìpẹ́ yìí, nígbà tí alálàyé kan ń kọ̀wé nípa bíborí ìdààmú àti àníyàn, ó sọ pé: “Ṣíṣàníyàn ń fi hàn pé a ò gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run.”
Orí ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ nínú Ìwàásù Lórí Òkè, pé, “ẹ dẹ́kun ṣíṣàníyàn” làwọn òǹkọ̀wé méjì yìí gbé ọ̀rọ̀ wọn kà. (Mátíù 6:25) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń ṣàníyàn lóde òní, a lè béèrè pé: Ṣó yẹ kí Kristẹni kan máa dá ara ẹ̀ lẹ́bi nítorí pé ó ń ṣàníyàn? Béèyàn bá ń ṣàníyàn, ṣé olúwarẹ̀ ò nígbàgbọ́ ni?
-
-
Ṣé Ẹní Bá Ń Ṣàníyàn Ò Nígbàgbọ́ Ni?Jí!—2004 | June 8
-
-
Ọlọ́run Mọ Àwọn Ohun Tá A Ṣaláìní
Ìwé Mímọ́ ràn wá lọ́wọ́ láti mọ ìyàtọ̀ tó wà láàárín àníyàn tó jẹ́ apá kan ìgbésí ayé ojoojúmọ́ àti ẹ̀ṣẹ̀ àìnígbàgbọ́. Ṣíṣàníyàn lójoojúmọ́ tàbí àìnígbàgbọ́ tó máa ń wáyé lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan nítorí àìlera ẹ̀dá yàtọ̀ pátápátá sí kíkọ̀ jálẹ̀ láti ní ìgbọ́kànlé nínú Ọlọ́run, èyí tó máa ń ti inú ọkàn-àyà burúkú, tó ti sébọ́ wá. Nítorí náà, kó yẹ kí ọkàn àwọn Kristẹni máa dá wọn lẹ́bi nígbà gbogbo ṣáá kìkì nítorí pé wọ́n máa ń ṣàníyàn lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan.
Bí ọ̀ràn tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, ó gba ìṣọ́ra o, kí àníyàn má bàa bò wá mọ́lẹ̀ búrúbúrú débi tí yóò fi máa darí ìgbésí ayé wa. Nítorí náà, ọgbọ́n wà nínú àwọn ọ̀rọ̀ tí Jésù sọ pé: “Ẹ má ṣàníyàn láé, kí ẹ sì wí pé, ‘Kí ni a ó jẹ?’ tàbí, ‘Kí ni a ó mu?’ tàbí, ‘Kí ni a ó wọ̀?’” Lẹ́yìn ìyẹn ló wá sọ̀rọ̀ ìtùnú yìí pé: “Nítorí Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run mọ̀ pé ẹ nílò gbogbo nǹkan wọ̀nyí. Ẹ máa bá a nìṣó, nígbà náà, ní wíwá ìjọba náà àti òdodo Rẹ̀ lákọ̀ọ́kọ́, gbogbo nǹkan mìíràn wọ̀nyí ni a ó sì fi kún un fún yín.”—Mátíù 6:25-33.
-