ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Oògùn Ajẹ́bíidán Fún Másùnmáwo
    Ilé Ìṣọ́—2001 | December 15
    • Ṣíṣiṣẹ́ Lábẹ́ Àjàgà Náà

      9, 10. Ní ayé ọjọ́un, àmì kí ni àjàgà jẹ́, èé sì ti ṣe tí Jésù fi sọ pé kí àwọn èèyàn gba àjàgà tòun sí ọrùn wọn?

      9 Ǹjẹ́ o ṣàkíyèsí pé nínú ọ̀rọ̀ tá a fà yọ látinú Mátíù 11:28, 29, Jésù sọ pé: “Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ mi.” Nígbà yẹn lọ́hùn-ún, àwọn gbáàtúù ti lè rí i pé abẹ́ àjàgà làwọn ti ń ṣiṣẹ́. Àtayébáyé ni àjàgà ti jẹ́ àmì ìsìnrú. (Jẹ́nẹ́sísì 27:40; Léfítíkù 26:13; Diutarónómì 28:48) Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń ṣe iṣẹ́ lébìrà nígbà ayé Jésù ló wà lábẹ́ àjàgà gidi, tí wọ́n ń gbé ẹrù wíwúwo. Bí wọ́n ṣe ṣe àjàgà ló máa pinnu bóyá ó máa rọni lọ́rùn tàbí ó máa dá egbò síni lọ́rùn àti léjìká. Níwọ̀n bí Jésù ti jẹ́ káfíńtà, ó ṣeé ṣe kó ti ṣe àjàgà rí, kó sì ti mọ bá a ṣe ń ṣe èyí tó máa ‘rọni lọ́rùn.’ Bóyá ńṣe ló lẹ awọ tàbí aṣọ mọ́ ibi tó ti máa kan ọrùn àti èjìká, kí àjàgà náà lè rọrùn-ún lò.

      10 Nígbà tí Jésù sọ pé, “Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín,” ó lè jẹ́ pé ńṣe ló ń fi ara rẹ̀ wé ẹni tí ń ṣe àwọn àjàgà tí wọ́n ṣe dáadáa, tí kò ní dá egbò sí ọrùn àti èjìká òṣìṣẹ́. Abájọ tí Jésù fi kún un pé: “Ẹrù mi sì fúyẹ́.” Èyí fi hàn pé àjàgà tó rọni lọ́rùn ni, iṣẹ́ náà kì í sì í ṣe àṣekúdórógbó. Òótọ́ ni pé pípè tí Jésù ń pe àwọn olùgbọ́ rẹ̀ pé kí wọ́n gba àjàgà òun sí ọrùn wọn kò túmọ̀ sí pé wọ́n á rí ìtura ojú ẹsẹ̀ kúrò nínú gbogbo ìnira tó ń bá àwọn èèyàn nígbà yẹn. Síbẹ̀, èròǹgbà tuntun tó gbé dé yóò mú ìtura ńláǹlà wá fún wọn. Àwọn àtúnṣe tí wọ́n bá ṣe nínú bí wọ́n ṣe ń gbé ìgbésí ayé wọn àti bí wọ́n ṣe ń ṣe nǹkan yóò mú ìtura wá fún wọn pẹ̀lú. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, ìrètí tó ṣe kedere, tó sì fẹsẹ̀ múlẹ̀ yóò jẹ́ kí másùnmáwo dín kù nínú ìgbésí ayé wọn.

      O Lè Rí Ìtura

      11. Kí nìdí tó fi jẹ́ pé kì í ṣe ọ̀ràn bíbọ́ àjàgà kan sílẹ̀ gbé òmíràn ni Jésù ń sọ?

      11 Jọ̀wọ́ ṣàkíyèsí pé Jésù kò sọ pé ṣe ni àwọn èèyàn á bọ́ àjàgà kan sílẹ̀ gbé òmíràn. Ilẹ̀ Róòmù ṣì wà lórí àlééfà síbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí àwọn ìjọba tòní ti wà lórí àlééfà níbi táwọn Kristẹni ń gbé. Owó orí tí ilẹ̀ Róòmù bù fáwọn èèyàn ní ọ̀rúndún kìíní ṣì wà níbẹ̀ digbí. Àìsàn àti ìṣòro ìṣúnná owó kò tíì kásẹ̀ nílẹ̀. Àìpé àti ẹ̀ṣẹ̀ ṣì ń da àwọn èèyàn láàmú. Síbẹ̀, nípa títẹ̀lé ẹ̀kọ́ Jésù wọ́n lè rí ìtura, gẹ́gẹ́ bí àwa náà ti lè rí ìtura lónìí.

      12, 13. Kí ni ohun pàtàkì tí Jésù sọ pé yóò mú ìtura wá, ìgbésẹ̀ wo sì ni àwọn kan gbé?

      12 Ohun tí àpèjúwe Jésù nípa àjàgà ń tọ́ka sí ní pàtàkì ni iṣẹ́ sísọni di ọmọ ẹ̀yìn. Kò sí àní-àní pé lájorí iṣẹ́ tí Jésù ṣe ni iṣẹ́ kíkọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́, ẹṣin ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ni Ìjọba Ọlọ́run. (Mátíù 4:23) Ìyẹn ló fi jẹ́ pé nígbà tó sọ pé, “Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín,” ó dájú pé èyí yóò wé mọ́ ṣíṣe irú iṣẹ́ tí òun ṣe. Níwọ̀n bí ọ̀rọ̀ iṣẹ́ ti máa ń kó ìdààmú bá ọ̀pọ̀ èèyàn, àwọn ìwé Ìhìn Rere fi hàn pé ọ̀rọ̀ Jésù mú káwọn olóòótọ́ ọkàn pa iṣẹ́ tí wọ́n ń ṣe tẹ́lẹ̀ tì, kí wọ́n sì mú iṣẹ́ míì ṣe. Rántí bó ṣe pe Pétérù, Áńdérù, Jákọ́bù àti Jòhánù pé: “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn, èmi yóò sì mú kí ẹ di apẹja ènìyàn.” (Máàkù 1:16-20) Ó jẹ́ kí àwọn apẹja wọ̀nyẹn mọ bí wọn yóò ṣe láyọ̀ tó, bí wọ́n bá ń ṣe iṣẹ́ tí òun fi sí ipò kìíní nínú ìgbésí ayé òun, ìyẹn bí wọ́n bá ń ṣe é lábẹ́ ìdarí òun àti pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òun.

      13 Ọ̀rọ̀ rẹ̀ yé àwọn kan lára àwọn Júù tó ń fetí sí i, wọ́n sì mú un lò. Ẹ fojú inú wo ohun tó ṣẹlẹ̀ lẹ́bàá òkun, gẹ́gẹ́ bí a ti ròyìn rẹ̀ nínú Lúùkù 5:1-11. Àwọn apẹja mẹ́rin ti fi gbogbo òru ṣe làálàá láìrí ẹja kankan pa. Àfẹ̀ẹ̀kan náà, tí àwọ̀n wọn kún bámú! Kò ṣàdédé rí bẹ́ẹ̀; iṣẹ́ ọwọ́ Jésù ni. Bí wọ́n ṣe yíjú sí etíkun, wọ́n rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ èèyàn tó ń hára gàgà láti gbọ́rọ̀ Jésù. Èyí jẹ́ ká mọ ìdí tí Jésù fi sọ fáwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin pé: ‘Láti ìsinsìnyí lọ, ẹ óò máa mú àwọn ènìyàn láàyè.’ Kí wá ni wọ́n ṣe? “Wọ́n dá àwọn ọkọ̀ náà padà wá sí ilẹ̀, wọ́n sì pa ohun gbogbo tì, wọ́n sì tẹ̀ lé e.”

      14. (a) Báwo la ṣe lè rí ìtura lónìí? (b) Kí ni ìhìn rere tí ń tuni lára tí Jésù kéde?

      14 Ìwọ náà lè gbé irú ìgbésẹ̀ yẹn. Iṣẹ́ kíkọ́ni ní òtítọ́ Bíbélì ṣì ń bá a lọ. Nǹkan bíi mílíọ̀nù mẹ́fà Ẹlẹ́rìí Jèhófà kárí ayé ti tẹ́wọ́ gba ìkésíni Jésù láti “gba àjàgà [rẹ̀] sọ́rùn” wọn; wọ́n sì ti di “apẹja ènìyàn.” (Mátíù 4:19) Àwọn kan ti sọ iṣẹ́ yìí di iṣẹ́ tí wọ́n ń fi ojoojúmọ́ ṣe; àwọn míì ń sa gbogbo ipá wọn láti máa ṣe é lóòrèkóòrè. Iṣẹ́ náà ń tu gbogbo wọn lára, ó sì ń tipa báyìí dín másùnmáwo kù. Ó jẹ́ ṣíṣe iṣẹ́ tó gbádùn mọ́ wọn, sísọ ìhìn rere fáwọn èèyàn—ìyẹn “ìhìn rere ìjọba náà.” (Mátíù 4:23) Nǹkan ayọ̀ ló máa ń jẹ́ láti sọ̀rọ̀ nípa ìhìn rere, àgàgà irú ìhìn rere yìí. Inú Bíbélì ní pàtàkì la ti lè rí ìsọfúnni tí yóò fi ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́kàn balẹ̀ pé wọ́n lè dín másùnmáwo inú ìgbésí ayé wọn kù.—2 Tímótì 3:16, 17.

      15. Báwo lo ṣe lè jàǹfààní látinú àwọn ẹ̀kọ́ tí Jésù kọ́ni nípa ìgbésí ayé?

      15 Títí dé àyè kan, kódà àwọn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ìjọba Ọlọ́run ti jàǹfààní nínú ẹ̀kọ́ Jésù nípa bí wọ́n ṣe lè gbé ìgbésí ayé wọn. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló lè fi tòótọ́tòótọ́ sọ pé ẹ̀kọ́ Jésù ti mú ìtura bá àwọn, ó sì ti tún ayé àwọn ṣe látòkèdélẹ̀. Ìgbésí ayé tìrẹ náà lè rí bẹ́ẹ̀, tó o bá ṣàyẹ̀wò àwọn ìlànà ìwà híhù tó wà nínú àkọsílẹ̀ nípa ìgbésí ayé Jésù àti iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, àgàgà àwọn ìwé Ìhìn Rere tí Mátíù, Máàkù àti Lúùkù kọ.

      Ọ̀nà Tá A Lè Gbà Rí Ìtura

      16, 17. (a) Ibo la ti lè rí lára àwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì tí Jésù fi kọ́ni? (b) Kí ni a ó ṣe bí a bá fẹ́ rí ìtura nípasẹ̀ fífi àwọn ẹ̀kọ́ Jésù sílò?

      16 Nígbà ìrúwé ọdún 31 Sànmánì Tiwa, Jésù sọ àsọyé kan tí òkìkí rẹ̀ ṣì ń kàn kárí ayé títí di òní olónìí. Àsọyé yìí ni wọ́n ń pè ní Ìwàásù Lórí Òkè. Ó wà nínú Mátíù orí karùn-ún sí ìkeje àti Lúùkù orí kẹfà. Ó jẹ́ àkópọ̀ ọ̀pọ̀ lára ẹ̀kọ́ rẹ̀. O tún lè rí àwọn ẹ̀kọ́ Jésù láwọn ibòmíràn nínú àwọn ìwé Ìhìn Rere. Ọ̀pọ̀ ohun tó sọ ló yéni yékéyéké, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lè ṣòroó fi ṣèwà hù. O ò ṣe fara balẹ̀ ka orí ìwé wọ̀nyẹn, kí o sì ronú lé wọn lórí? Jẹ́ kí agbára ọ̀rọ̀ rẹ̀ máa darí èrò àti ìṣe rẹ.

      17 Onírúurú ìsọ̀rí la lè pín àwọn ẹ̀kọ́ Jésù sí. Ẹ jẹ́ ká kó àwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì jọ sójú kan, kí ọ̀kọ̀ọ̀kan lè wà fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú oṣù, kí o sì pinnu láti máa fi wọ́n sílò nínú ìgbésí ayé rẹ. Lọ́nà wo? Tóò, má kàn wò wọ́n gààràgà. Rántí ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso, tó béèrè lọ́wọ́ Jésù Kristi pé: “Nípa ṣíṣe kí ni èmi yóò fi jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” Nígbà tí Jésù rán an létí àwọn ohun pàtàkì tí Òfin Ọlọ́run là sílẹ̀, ọkùnrin náà fèsì pé gbogbo rẹ̀ lòun ń pa mọ́. Síbẹ̀, ó rí i pé ó ṣì ku àwọn nǹkan kan. Jésù ní kí ó túbọ̀ sapá láti fi àwọn ìlànà Ọlọ́run sílò lọ́nà tó gbéṣẹ́, kí ó di ọmọlẹ́yìn gidi. Àmọ́ ọkùnrin yìí kò múra tán láti ṣe gbogbo ìyẹn. (Lúùkù 18:18-23) Nítorí náà, ó yẹ kí ẹni tó bá fẹ́ tẹ̀ lé ẹ̀kọ́ Jésù lónìí rántí pé ìyàtọ̀ wà láàárín wíwulẹ̀ tẹ́wọ́ gba ẹ̀kọ́ Jésù àti mímú wọn lò ní ti gidi, kí onítọ̀hún lè dín másùnmáwo kù.

      18. Ṣàlàyé bí àpótí tó wà nínú àpilẹ̀kọ yìí ṣe lè ṣàǹfààní fún ọ.

      18 Bí o ṣe fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ṣíṣàyẹ̀wò àti fífi àwọn ẹ̀kọ́ Jésù sílò, wo kókó àkọ́kọ́ nínú àpótí tó wà nínú àpilẹ̀kọ yìí. Ó tọ́ka sí Mátíù 5:3-9. Ní ti gidi, ẹnikẹ́ni nínú wa lè lo ọ̀pọ̀ àkókò láti ṣe àṣàrò lórí ìmọ̀ràn alárinrin tó wà nínú ẹsẹ wọ̀nyẹn. Ṣùgbọ́n tó o bá wo gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, èrò wo lo máa ní nípa irú ẹ̀mí tó yẹ kéèyàn ní? Tó bá jẹ́ pé lóòótọ́ lo fẹ́ bọ́ lọ́wọ́ àpọ̀jù másùnmáwo nínú ìgbésí ayé rẹ, kí ni yóò ràn ọ́ lọ́wọ́? Báwo ni ayé rẹ ṣe lè sunwọ̀n sí i nípa títúbọ̀ gbájú mọ́ nǹkan tẹ̀mí, ìyẹn ni pé kó o jẹ́ kí nǹkan tẹ̀mí gbà ọ́ lọ́kàn? Ǹjẹ́ àwọn nǹkan kan wà nínú ìgbésí ayé rẹ tí kò yẹ kó gbà ọ́ lọ́kàn jù, kó o lè túbọ̀ ráyè gbájú mọ́ àwọn nǹkan tẹ̀mí? Bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò fi kún ayọ̀ rẹ nísinsìnyí.

      19. Kí lo lè ṣe láti jèrè ìmọ̀ àti òye púpọ̀ sí i?

      19 Wàyí o, má fi mọ síbẹ̀ yẹn. O ò ṣe jíròrò ẹsẹ wọ̀nyẹn pẹ̀lú ẹlòmíràn tó jẹ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run, bóyá ọkọ tàbí aya rẹ, ìbátan rẹ, tàbí ọ̀rẹ́ rẹ? (Òwe 18:24; 20:5) Rántí pé ọlọ́rọ̀ tó jẹ́ olùṣàkóso náà béèrè irú ọ̀rọ̀ tí à ń sọ yìí lọ́wọ́ ẹlòmíràn—ìyẹn Jésù. Èsì tó fún un ì bá fi kún ayọ̀ rẹ̀ àti ìrètí rẹ̀ fún ìyè pípẹ́ títí. Olùjọsìn ẹlẹgbẹ́ rẹ tó o fẹ́ bá jíròrò ẹsẹ wọ̀nyẹn kò lè mọ̀ tó Jésù; síbẹ̀, jíjíròrò nípa àwọn ẹ̀kọ́ Jésù yóò ṣe ẹ̀yin méjèèjì láǹfààní. Gbìyànjú láti tètè ṣe é.

      20, 21. Ìtòlẹ́sẹẹsẹ wo lo lè tẹ̀ lé láti fi mọ àwọn ẹ̀kọ́ Jésù, báwo lo sì ṣe lè mọ bó o ṣe ń tẹ̀ síwájú sí?

      20 Tún wo àpótí náà, “Àwọn Ẹ̀kọ́ Tí Yóò Ràn Ọ́ Lọ́wọ́.” A ṣètò ẹ̀kọ́ wọ̀nyí lọ́nà tí wàá fi rí ó kéré tán, ẹ̀kọ́ kan, tí wàá máa ronú lé lóòjọ́. O lè kọ́kọ́ lọ ka ohun tí Jésù sọ nínú àwọn ẹsẹ tá a tọ́ka sí. Lẹ́yìn náà, wáá ronú lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀. Ronú jinlẹ̀ lórí bó o ṣe lè fi wọ́n sílò nínú ìgbésí ayé rẹ. Bó o bá gbà pé o ti ń fi wọ́n sílò, ronú lórí nǹkan míì tó o tún lè ṣe láti túbọ̀ fi ẹ̀kọ́ Ọlọ́run náà ṣèwà hù. Gbìyànjú láti fi ẹ̀kọ́ yẹn sílò lọ́jọ́ yẹn. Bó bá gbà ẹ́ lákòókò láti lóye rẹ̀ tàbí láti mọ bó o ṣe lè fi í sílò, lo ọjọ́ kan sí i lórí ẹ̀kọ́ yẹn. Ṣùgbọ́n o, rántí pé kò dìgbà tó bá mọ́ ọ lára tán kó o tó kọjá lọ sórí ẹ̀kọ́ tó tẹ̀ lé e. O lè gbé ẹ̀kọ́ mìíràn yẹ̀ wò lọ́jọ́ tó tẹ̀ lé e. Nígbà tí ọ̀sẹ̀ yẹn bá parí, o lè ṣàtúnyẹ̀wò bó o ti kẹ́sẹ járí tó nínú fífi ẹ̀kọ́ mẹ́rin tàbí márùn-ún lára àwọn ẹ̀kọ́ Jésù ṣèwà hù. Ní ọ̀sẹ̀ kejì, fi àwọn ẹ̀kọ́ mìíràn kún un, lójoojúmọ́. Bó bá ṣẹlẹ̀ pé o fìdí rẹmi nínú fífi ẹ̀kọ́ kan sílò, má jọ̀gọ̀ nù. Kò sí Kristẹni tí irú ìyẹn kì í ṣẹlẹ̀ sí. (2 Kíróníkà 6:36; Sáàmù 130:3; Oníwàásù 7:20; Jákọ́bù 3:8) Má a bá a lọ ní ọ̀sẹ̀ kẹta àti ọ̀sẹ̀ kẹrin.

      21 Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù kan, ó ṣeé ṣe kó o ti kárí gbogbo kókó mọ́kànlélọ́gbọ̀n náà. Tóò, ìyàtọ̀ wo lo máa rí? Ǹjẹ́ o ò ní láyọ̀ sí i, ǹjẹ́ ọkàn rẹ ò sì ní balẹ̀ sí i? Ká tiẹ̀ sọ pé kìkì àtúnṣe bín-ń-tín lo ṣe, wàá rí i pé másùnmáwo tó o máa ń ní á dín kù, tàbí ó kéré tán, wàá lè kojú rẹ̀ nísinsìnyí, wàá sì mọ bí wàá ṣe máa bá a yí. Má gbàgbé pé àwọn kókó púpọ̀ tó wúlò gan-an ṣì wà nínú ẹ̀kọ́ Jésù tí a kò tò sínú àpótí yìí. O ò ṣe wá wọn kàn, kí o sì gbìyànjú láti fi wọ́n sílò?—Fílípì 3:16.

      22. Kí ni ó lè jẹ́ àbájáde títẹ̀lé ẹ̀kọ́ Jésù, àmọ́ apá mìíràn wo ló tún yẹ ká gbé yẹ̀ wò?

      22 Wàá rí i pé àjàgà Jésù rọni lọ́rùn lóòótọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní ọ̀rìn tiẹ̀. Ẹrù títẹ̀lé àwọn ẹ̀kọ́ rẹ̀ àti jíjẹ́ ọmọlẹ́yìn rẹ̀ fúyẹ́. Lẹ́yìn ohun tó lé ní ọgọ́ta ọdún tí àpọ́sítélì Jòhánù, tó jẹ́ ọ̀rẹ́ Jésù ọ̀wọ́n, ti ń gbé àjàgà ọ̀hún, ó sọ pé: “Èyí ni ohun tí ìfẹ́ fún Ọlọ́run túmọ̀ sí, pé kí a pa àwọn àṣẹ rẹ̀ mọ́; síbẹ̀ àwọn àṣẹ rẹ̀ kì í ṣe ẹrù ìnira.” (1 Jòhánù 5:3) Ìwọ náà lè gbà pé bó ṣe rí gẹ́ẹ́ nìyẹn. Bó o bá ṣe túbọ̀ ń fi ẹ̀kọ́ Jésù ṣèwà hù, bẹ́ẹ̀ náà ni wàá túbọ̀ máa rí i pé ohun tó ń mú kí ìgbésí ayé ọ̀pọ̀ èèyàn kún fún másùnmáwo lónìí kò ní kó hílàhílo bá ọ. Wàá rí i pé o ti rí ìtura ńláǹlà. (Sáàmù 34:8) Àmọ́, nǹkan míì tún wà nípa àjàgà rírọrùn Jésù tó yẹ kó o gbé yẹ̀ wò. Jésù tún sọ pé “onínú tútù àti ẹni rírẹlẹ̀ ní ọkàn-àyà” ni òun. Báwo ni ìyẹn ṣe wé mọ́ kíkẹ́kọ̀ọ́ lára Jésù àti fífara wé e? A óò gbé èyí yẹ̀ wò nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé e.—Mátíù 11:29.

  • ‘Ẹ Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Mi’
    Ilé Ìṣọ́—2001 | December 15
    • ‘Ẹ Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Mi’

      “Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ mi, nítorí onínú tútù àti ẹni rírẹlẹ̀ ní ọkàn-àyà ni èmi, ẹ ó sì rí ìtura fún ọkàn yín.”—MÁTÍÙ 11:29.

      1. Èé ṣe tí kíkẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ Jésù fi lè máyọ̀ wá, kí ó sì mú kí ayé wa dùn bí oyin?

      JÉSÙ KRISTI máa ń ronú, ó máa ń kọ́ni, ó sì máa ń gbégbèésẹ̀ tó tọ́ nígbà gbogbo. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọdún díẹ̀ ló lò láyé, síbẹ̀ ó gbélé ayé ṣe ohun rere, tó fún un ní ìtẹ́lọ́rùn, tó sì mú ayọ̀ rẹ̀ kún. Ó kó àwọn ọmọ ẹ̀yìn jọ, ó kọ́ wọn nípa bí wọ́n ṣe lè sin Ọlọ́run, bí wọ́n ṣe lè nífẹ̀ẹ́ aráyé àti bí wọ́n ṣe lè ṣẹ́gun ayé. (Jòhánù 16:33) Ó fi ìrètí kún ọkàn wọn, ó sì “tan ìmọ́lẹ̀ sórí ìyè àti àìdíbàjẹ́ nípasẹ̀ ìhìn rere.” (2 Tímótì 1:10) Tó o bá wà lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, kí lo rò pé ó túmọ̀ sí láti jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn? Ẹ jẹ́ ká gbé ohun tí Jésù sọ nípa ọmọ ẹ̀yìn yẹ̀ wò, ìyẹn á mú kí ayé wa dùn bí oyin. Èyí wé mọ́ níní èrò kan náà tí òun ní àti títẹ̀lé àwọn ìlànà pàtàkì kan.—Mátíù 10:24, 25; Lúùkù 14:26, 27; Jòhánù 8:31, 32; 13:35; 15:8.

      2, 3. (a) Kí ló túmọ̀ sí láti jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Jésù? (b) Èé ṣe tó fi ṣe pàtàkì láti bi ara wa pé, ‘Ọmọ ẹ̀yìn ta lèmi jẹ́?’

      2 Nínú Ìwé Mímọ́ Kristẹni Lédè Gíríìkì, ohun tí ọ̀rọ̀ tá a tú sí “ọmọ ẹ̀yìn” túmọ̀ sí gan-an ni ẹni tí ń fọkàn sí nǹkan kan, tàbí akẹ́kọ̀ọ́. Ọ̀rọ̀ kan tó fara pẹ́ ẹ wà nínú ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a gbé àpilẹ̀kọ yìí kà, èyíinì ni Mátíù 11:29, tó kà pé: “Ẹ gba àjàgà mi sọ́rùn yín, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ mi, nítorí onínú tútù àti ẹni rírẹlẹ̀ ní ọkàn-àyà ni èmi, ẹ ó sì rí ìtura fún ọkàn yín.” Bẹ́ẹ̀ ni o, èyí fi hàn pé ẹni tí ń kẹ́kọ̀ọ́ ni ọmọ ẹ̀yìn jẹ́. Àwọn ìwé Ìhìn Rere sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ náà “ọmọ ẹ̀yìn” fún àwọn tó ń tọ Jésù lẹ́yìn tímọ́tímọ́, tí wọ́n ń bá a rìnrìn àjò bó ṣe ń wàásù kiri, tí wọ́n sì ń gba ìtọ́ni látọ̀dọ̀ rẹ̀. Àwọn kan lè wulẹ̀ fara mọ́ àwọn ẹ̀kọ́ Jésù, bóyá ní bòókẹ́lẹ́ pàápàá. (Lúùkù 6:17; Jòhánù 19:38) Àwọn tó kọ ìwé Ìhìn Rere tún sọ̀rọ̀ nípa “àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jòhánù [Oníbatisí] àti àwọn ọmọ ẹ̀yìn àwọn Farisí.” (Máàkù 2:18) Níwọ̀n bí Jésù ti kìlọ̀ fáwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ pé “kí wọ́n ṣọ́ra . . . fún ẹ̀kọ́ àwọn Farisí,” a lè béèrè lọ́wọ́ ara wa pé, ‘Ọmọ ẹ̀yìn ta lèmi jẹ́?’—Mátíù 16:12.

      3 Bó bá jẹ́ pé ọmọ ẹ̀yìn Jésù ni wá, bó bá jẹ́ pé a ti kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ rẹ̀, ó yẹ kí ara máa tu àwọn èèyàn nípa tẹ̀mí nígbà tí wọ́n bá wà ní sàkáání wa. Ó yẹ kí wọ́n rí wa bí ẹni tó ti túbọ̀ jẹ́ ẹni pẹ̀lẹ́ àti onírẹ̀lẹ̀ ju ti tẹ́lẹ̀ lọ. Bá a bá jẹ́ ọ̀gá níbi iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ wa, bá a bá jẹ́ òbí, tàbí bá a bá jẹ́ ẹni tó ní ẹrù iṣẹ́ olùṣọ́ àgùntàn nínú ìjọ Kristẹni, ǹjẹ́ àwọn tó wà lábẹ́ àbójútó wa lè gba ẹ̀rí wa jẹ́, pé à ń tọ́jú àwọn gẹ́gẹ́ bí Jésù ṣe ń tọ́jú àwọn tó wà lábẹ́ àbójútó rẹ̀?

      Ọwọ́ Tí Jésù Fi Mú Àwọn Èèyàn

      4, 5. (a) Kí nìdí tí kò fi ṣòro láti mọ irú ọwọ́ tí Jésù fi mú àwọn èèyàn tó wà nínú ìṣòro? (b) Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Jésù lọ jẹun nínú ilé Farisí kan?

      4 Ó yẹ ká mọ ọwọ́ tí Jésù fi mú àwọn èèyàn, àgàgà àwọn tó wà nínú ìṣòro líle koko. Ìyẹn ò ṣòroó mọ̀; torí pé ìtàn pọ̀ nínú Bíbélì tó dá lórí àjọṣe àárín Jésù àtàwọn ẹlòmíì. Àwọn kan lára wọn sì jẹ́ àwọn tí ìpọ́njú dé bá. Ẹ tún jẹ́ ká kíyè sí ọwọ́ tí àwọn aṣáájú ẹ̀sìn, àgàgà àwọn Farisí, fi mú àwọn èèyàn tó ní irú ìṣòro kan náà. A óò rí ẹ̀kọ́ kọ́ nínú kíkíyèsí ìyàtọ̀ tó wà láàárín wọn.

      5 Lọ́dún 31 Sànmánì Tiwa, nígbà tí Jésù wà lẹ́nu iṣẹ́ wíwàásù ní Gálílì, “ẹnì kan nínú àwọn Farisí ń rọ [Jésù] ṣáá láti bá òun jẹun.” Jésù kò kọ ìkésíni náà. “Ní ìbámu pẹ̀lú èyí, ó wọ ilé Farisí náà, ó sì rọ̀gbọ̀kú nídìí tábìlì. Sì wò ó! obìnrin kan tí a mọ̀ sí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ìlú ńlá náà gbọ́ pé ó ń rọ̀gbọ̀kú nídìí oúnjẹ nínú ilé Farisí náà, ó sì mú orùba alabásítà òróró onílọ́fínńdà wá, àti, ní bíbọ́ sí ipò kan lẹ́yìn lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sunkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi omijé rẹ̀ rin ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ̀ nù ún kúrò. Pẹ̀lúpẹ̀lù, ó fi ẹnu ko ẹsẹ̀ rẹ̀ lọ́nà jẹ̀lẹ́ńkẹ́, ó sì fi òróró onílọ́fínńdà náà pa á.”—Lúùkù 7:36-38.

      6. Báwo ni obìnrin kan tó jẹ́ “ẹlẹ́ṣẹ̀” ṣe ráyè wọlé Farisí náà?

      6 Ǹjẹ́ o lè fojú inú wo ìṣẹ̀lẹ̀ yẹn? Ìwé kan tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ sọ pé: “Obìnrin náà (ẹsẹ 37) lo àǹfààní àṣà ìbílẹ̀ wọn tó fàyè gba àwọn aláìní láti wá síbi irú àsè bẹ́ẹ̀ láti wá gba àjẹkù oúnjẹ.” Bóyá ìdí nìyẹn tẹ́nì kan fi lè ráyè wọlé láìjẹ́ pé a pè é. Àwọn míì tún lè wà tí wọ́n á fẹ́ wá re àjẹkù jọ lẹ́yìn àsè. Àmọ́, ọ̀tọ̀ ni ohun tí obìnrin yìí bá wá. Kò ṣe bí àwọn mo-gbọ́-mo-yà, tó ń retí kí àsè parí. Kò lórúkọ rere ládùúgbò. “Ẹlẹ́ṣẹ̀” paraku ni, tó bẹ́ẹ̀ tí Jésù fi sọ pé òun mọ̀ pé ‘àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ pọ̀.’—Lúùkù 7:47.

      7, 8. (a) Kí ni ó ṣeé ṣe ka sọ, bá a bá rí ara wa nínú irú ipò tí ìwé Lúùkù 7:36-38 ròyìn? (b) Kí ni Símónì sọ?

      7 Ká sọ pé o wà láyé nígbà yẹn lọ́hùn-ún, tó o sì wà nípò tí Jésù wà. Kí lò bá ṣe? Ṣé ojú ò ní tì ọ́ bí obìnrin yìí ti ń bọ̀ lọ́dọ̀ rẹ? Kí ni wíwà nínú irú ipò bẹ́ẹ̀ ì bá sún ọ ṣe? (Lúùkù 7:45) Ǹjẹ́ orí rẹ ò ní fẹ́rẹ̀ẹ́ fò lọ, àní ǹjẹ́ àyà rẹ ò ní já?

      8 Ká ní ọ̀kan lára àwọn àlejò ni ọ́, ó kéré tán ǹjẹ́ èrò rẹ máa fara pẹ́ ti Símónì tí í ṣe Farisí? “Ní rírí èyí, Farisí tí ó ké sí [Jésù] sọ nínú ara rẹ̀ pé: ‘Ọkùnrin yìí, bí ó bá jẹ́ wòlíì ni, ì bá mọ ẹni àti irú obìnrin tí ẹni tí ń fọwọ́ kan òun jẹ́, pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.’” (Lúùkù 7:39) Ní ìyàtọ̀ pátápátá sí èyí, ojú àánú Jésù pọ̀. Ó rí ipò ìbànújẹ́ tí obìnrin náà wà. Ó rí i pé làásìgbò ti bá a. A ò mọ bí obìnrin náà ṣe di ẹrú ẹ̀ṣẹ̀. Bó bá jẹ́ pé aṣẹ́wó lobìnrin náà lóòótọ́, á jẹ́ pé àwọn Júù olùfọkànsìn, tí wọ́n jẹ́ aráàlú yẹn kò ràn án lọ́wọ́.

      9. Kí ni Jésù sọ, kí ni ó sì ṣeé ṣe kí ó jẹ́ àbájáde rẹ̀?

      9 Ṣùgbọ́n Jésù fẹ́ ràn án lọ́wọ́. Ó sọ fún obìnrin náà pé: “A dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì.” Ó wá fi kún un pé: “Ìgbàgbọ́ rẹ ti gbà ọ́ là; máa bá ọ̀nà rẹ lọ ní àlàáfíà.” (Lúùkù 7:48-50) Ibi tí ìtàn yẹn parí sí nìyẹn. Ẹnì kan lè sọ pé òun ò rò pé Jésù ran obìnrin náà lọ́wọ́ lọ títí. Ó kéré tán, ó súre fún un. Ṣé o rò pé ó tún padà sídìí ìranù tó ń ṣe tẹ́lẹ̀? Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ò mọ̀ dájú, ṣàkíyèsí ohun tí Lúùkù sọ tẹ̀ lé e. Ó ṣàlàyé pé Jésù “ń rin ìrìn àjò lọ láti ìlú ńlá dé ìlú ńlá àti láti abúlé dé abúlé, ó ń wàásù, ó sì ń polongo ìhìn rere ìjọba Ọlọ́run.” Lúùkù tún ròyìn pé “àwọn obìnrin kan” wà pẹ̀lú Jésù àtàwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, tí wọ́n “ń ṣèránṣẹ́ fún wọn láti inú àwọn nǹkan ìní” àwọn obìnrin náà. Ó ṣeé ṣe kí obìnrin tó ti ronú pìwà dà, tó sì moore yìí wà lára wọn, kó ti bẹ̀rẹ̀ sí í gbé ìgbé ayé tó bá ìfẹ́ Ọlọ́run mu pẹ̀lú ẹ̀rí ọkàn tó mọ́, pẹ̀lú ète gúnmọ́ nínú ìgbésí ayé àti pẹ̀lú ìfẹ́ jíjinlẹ̀ fún Ọlọ́run.—Lúùkù 8:1-3.

      Ìyàtọ̀ Tó Wà Láàárín Jésù Àtàwọn Farisí

      10. Èé ṣe tó fi dáa pé ká gbé ohun tó ṣẹlẹ̀ láàárín Jésù àti obìnrin kan nílé Símónì yẹ̀ wò?

      10 Ẹ̀kọ́ wo la lè rí kọ́ nínú ìtàn tó fakíki yìí? Ó wọ̀ wá lọ́kàn ṣinṣin, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́? Ká sọ pé o wà nílé Símónì lọ́jọ́ tá a ń wí yìí. Kí lò bá ṣe? Ṣé ohun tí Jésù ṣe lò bá ṣe, tàbí wàá ṣe bíi Farisí tó gba àlejò? A mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run ni Jésù, nítorí náà ọwọ́ tí a máa fi mú ọ̀ràn náà àti ìgbésẹ̀ tá a máa gbé lè máà bá tirẹ̀ mu gẹ́lẹ́. Àmọ́, a lè fọwọ́ sọ̀yà pé àwa ò ní ṣe bíi Símónì, Farisí. Ṣàṣà lẹni tó máa fẹ́ ká pe òun ní Farisí.

      11. Èé ṣe tí a kò fi ní fẹ́ kí wọ́n kà wá mọ́ àwọn Farisí?

      11 Látinú ohun tí Bíbélì àtàwọn ìwé ayé sọ, ó dájú pé àwọn Farisí jọ ara wọn lójú bí nǹkan míì. Kódà wọ́n sọ pé àwọn ni ẹgbẹ́ má-jẹ̀ẹ́-ó-bà-jẹ́ tó ń bójú tó ire àwọn aráàlú àti ti orílẹ̀-èdè náà. Bí Òfin Ọlọ́run ṣe ṣe kedere, tó sì yéni yékéyéké yẹn kò tẹ́ wọn lọ́rùn rárá. Nígbà tí Òfin náà kò bá sojú abẹ níkòó tó lójú tiwọn, kíá ni wọ́n á lọ gbé òfin awúrúju kan kalẹ̀, láti fi dí ohun tí wọ́n pè ní àlàfo, kí ẹ̀rí ọkàn àwọn èèyàn má bàa wúlò mọ́ rárá. Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn wọ̀nyí bá a débi pé wọ́n fẹ́ ṣòfin lórí gbogbo ìgbòkègbodò ẹ̀dá, àní lórí àwọn ohun tí kò tó nǹkan pàápàá.a

      12. Irú ojú wo làwọn Farisí fi ń wo ara wọn?

      12 Òpìtàn ọ̀rúndún kìíní nì, Josephus, tí í ṣe Júù, sọ pé àwọn Farisí máa ń fi yé àwọn èèyàn pé àwọn jẹ́ onínúure, oníwà pẹ̀lẹ́, aláìṣègbè àti pé àwọn dáńgájíá fún iṣẹ́ tí àwọn ń ṣe. Lóòótọ́, àwọn kan nínú wọn lè rí báyẹn títí dé àyè kan. Bóyá ọkàn rẹ lọ sọ́dọ̀ Nikodémù. (Jòhánù 3:1, 2; 7:50, 51) Bí àkókò ti ń lọ, àwọn díẹ̀ lára wọn di Kristẹni. (Ìṣe 15:5) Kristẹni àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé nípa àwọn Júù kan, irú bí àwọn Farisí, pé: “Wọ́n ní ìtara fún Ọlọ́run; ṣùgbọ́n kì í ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ìmọ̀ pípéye.” (Róòmù 10:2) Àmọ́ ṣá o, bí wọ́n ṣe rí lójú àwọn mùtúmùwà ni àwọn ìwé Ìhìn Rere sọ—wọ́n jẹ́ agbéraga, ajọra-ẹni-lójú, olódodo lójú ara ẹni, alárìíwísí, aláìgbatẹnirò àti pẹ̀gànpẹ̀gàn.

      Ojú Tí Jésù Fi Ń Wò Wọ́n

      13. Kí ni Jésù sọ nípa àwọn Farisí?

      13 Jésù na àwọn akọ̀wé àtàwọn Farisí ní patiyẹ ọ̀rọ̀. Ó ní alágàbàgebè ni wọ́n. Ó sọ pé: “Wọ́n di àwọn ẹrù wíwúwo, wọ́n sì gbé wọn lé èjìká àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àwọn tìkára wọn kò fẹ́ láti fi ìka wọn sún wọn kẹ́rẹ́.” Lóòótọ́ ni ẹrù ọ̀hún wúwo, àjàgà kànńpá sì ni wọ́n gbé kọ́ àwọn èèyàn lọ́rùn. Jésù tún pe àwọn akọ̀wé àtàwọn Farisí ní “òmùgọ̀.” A sì mọ̀ pé òmùgọ̀ lè kó àwọn ará àdúgbò sí yọ́ọ́yọ́ọ́. Jésù tún pe àwọn akọ̀wé àtàwọn Farisí ní “afọ́jú afinimọ̀nà,” ó sì là á mọ́lẹ̀ pé wọ́n “ṣàìka àwọn ọ̀ràn wíwúwo jù lọ nínú Òfin sí, èyíinì ni, ìdájọ́ òdodo àti àánú àti ìṣòtítọ́.” Ta ló máa fẹ́ kí Jésù ka òun sí Farisí?—Mátíù 23:1-4, 16, 17, 23.

      14, 15. (a) Àjọṣe tí Jésù ní pẹ̀lú Mátíù Léfì fi kí ni hàn nípa irú èèyàn táwọn Farisí jẹ́? (b) Ẹ̀kọ́ pàtàkì wo la lè rí kọ́ nínú ìtàn yìí?

      14 Ṣàṣà lẹni tó ń ka àwọn ìtàn inú ìwé Ìhìn Rere tí kò ní rí i pé alárìíwísí gbáà lèyí tó pọ̀ jù lára àwọn Farisí. Lẹ́yìn tí Jésù ké sí Mátíù Léfì, tí í ṣe agbowó orí, pé kí ó wá di ọmọ ẹ̀yìn òun, Léfì filé pọntí, ó fọ̀nà rokà, nítorí Jésù. Àkọsílẹ̀ náà sọ pé: “Látàrí èyí, àwọn Farisí àti àwọn akọ̀wé òfin wọn bẹ̀rẹ̀ sí kùn sí àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀, pé: ‘Èé ṣe tí ó fi jẹ́ pé ẹ ń jẹ, ẹ sì ń mu pẹ̀lú àwọn agbowó orí àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀?’ Ní ìfèsìpadà, Jésù wí fún wọn pé: ‘. . . Èmi kò wá láti pe àwọn olódodo bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sí ìrònúpìwàdà.’”—Lúùkù 5:27-32.

      15 Léfì alára mọrírì ọ̀rọ̀ kan tí Jésù sọ níbẹ̀ yẹn, pé: “Ẹ lọ, nígbà náà, kí ẹ sì kẹ́kọ̀ọ́ ohun tí èyí túmọ̀ sí, ‘Àánú ni èmi fẹ́, kì í sì í ṣe ẹbọ.’” (Mátíù 9:13) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn Farisí sọ pé àwọn gba ìwé àwọn wòlíì Hébérù gbọ́, wọn ò gba ọ̀rọ̀ tó wá látinú Hóséà 6:6 yìí gbọ́. Lójú tiwọn, rírinkinkin mọ́ òfin ṣe pàtàkì ju níní ojú àánú lọ. Kálukú wá lè béèrè lọ́wọ́ ara rẹ̀ pé, ‘Ṣé n kì í rinkinkin mọ́ àwọn ìlànà jù, pàápàá tó bá jẹ́ èyí tó dá lórí èrò ti ara ẹni tàbí àwọn ọ̀ràn èyí-wù-mí-ò-wù-ọ́? Tàbí kẹ̀, ṣé aláàánú àti onínúure làwọn èèyàn mọ̀ mí sí?’

      16. Kí ni ìwà àwọn Farisí, báwo la sì ṣe lè yàgò fún dídàbí wọn?

      16 Àríwísí, àríwísí, àríwísí ṣáá ni. Àwọn Farisí ò mọ̀ jùyẹn lọ. Ńṣe làwọn Farisí ń wá àléébù kiri—ì báà jẹ́ àléébù gidi, tàbí ohunkóhun tí wọ́n bá rò pé ó jẹ́ àléébù. Ohun táwọn èèyàn ń ṣe tó kù díẹ̀ káàtó nìkan ni wọ́n ń rí sọ ṣáá. Àwọn Farisí ń yangàn pé àwọn ń san ìdámẹ́wàá ewébẹ̀ tó kéré jù lọ, bí efinrin, dílì àti kúmínì. Wọ́n ń gbé aṣọ gẹ̀rẹ̀jẹ̀-gẹ̀rẹ̀jẹ̀ wọ̀ láti fi ṣe kárími níbi ìjọsìn. Wọ́n sì ń ṣe ìṣe àwa-la-wà-ńbẹ̀ nínú ọ̀ràn orílẹ̀-èdè. Láìsí àní-àní, bí ìṣesí wa yóò bá bá àpẹẹrẹ Jésù mu, a ó yàgò fún ẹ̀mí wíwá àléébù kiri.

      Báwo Ni Jésù Ṣe Ń Yanjú Ìṣòro?

      17-19. (a) Ṣàlàyé bí Jésù ṣe yanjú ọ̀ràn kan tí ì bá di ńlá. (b) Kí ló mú kí ipò náà jẹ́ èyí tí kò fara rọ, tí kò sì bára dé rárá? (d) Ká ní o wà níbẹ̀ nígbà tí obìnrin náà tọ Jésù wá ni, kí lò bá ṣe?

      17 Bí Jésù ṣe ń yanjú ìṣòro yàtọ̀ pátápátá sí bí àwọn Farisí ṣe ń yanjú rẹ̀. Ẹ jẹ́ ká wo bí Jésù ṣe yanjú ọ̀ràn kan tí ì bá di wàhálà ńlá. Obìnrin kan mà ni o, tí ó ti ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọdún méjìlá gbáko. O lè ka ìtàn náà ní Lúùkù 8:42-48.

      18 Àkọsílẹ̀ Máàkù sọ pé ‘jìnnìjìnnì bá obìnrin náà, ó sì ń wárìrì.’ (Máàkù 5:33) Èé ṣe? Nítorí ó mọ̀ pé òun ti rú Òfin Ọlọ́run. Léfítíkù 15:25-28 sọ pé obìnrin tí ẹ̀jẹ̀ bá ń sun lára rẹ̀ lódìlódì jẹ́ aláìmọ́ ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà bá ń sun, yóò sì tún wà ní aláìmọ́ lọ́sẹ̀ kan lẹ́yìn náà. Gbogbo nǹkan, àti gbogbo ẹni tí ara rẹ̀ bá kàn yóò di aláìmọ́. Kí obìnrin yìí lè dé ọ̀dọ̀ Jésù, ó forí la ọ̀nà gba àárín ogunlọ́gọ̀ kọjá. Tá a bá ka àkọsílẹ̀ náà lónìí, ní ẹgbẹ̀rún ọdún méjì lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ náà, àánú rẹ̀ ò ní ṣàìṣe wá nítorí ohun tó ti ń rún mọ́ra.

      19 Ká ní o wà níbẹ̀ lọ́jọ́ yẹn ni, ojú wo lò bá fi wo ohun tó ṣẹlẹ̀ yẹn? Kí lò bá sọ? Wàá rí i pé Jésù káàánú obìnrin yìí, ó hùwà sí i tìfẹ́tìfẹ́, ó sì gba tirẹ̀ rò. Àní kò tiẹ̀ mẹ́nu kan wàhálà tó ṣeé ṣe kó ti dá sílẹ̀.—Máàkù 5:34.

      20. Ká sọ pé òfin inú Léfítíkù 15:25-28 kàn wá lónìí, irú ipò wo ló ṣeé ṣe kó dojú kọ wá?

      20 Ǹjẹ́ a lè rí ẹ̀kọ́ kọ́ nínú ìṣẹ̀lẹ̀ yìí? Ká sọ pé alàgbà ni ọ́ nínú ìjọ Kristẹni lónìí. Ká tún sọ pé òfin inú Léfítíkù 15:25-28 yẹn kan àwa Kristẹni lónìí. Ó sì wá ṣẹlẹ̀ pé obìnrin kan tó jẹ́ Kristẹni ti rú òfin yẹn. Àmọ́ ara rẹ̀ ò wá lélẹ̀ mọ́. Ó sì ń wò tàánútàánú. Kí ni wàá ṣe? Ṣé o ò ní nà án lẹ́gba ọ̀rọ̀ níṣojú gbogbo èrò títí á fi kárí sọ? O lè fèsì pé: “Áà, ó tì o, mi ò jẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀! Àpẹẹrẹ Jésù ni màá tẹ̀ lé. Màá rí i dájú pé mo ṣe é jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́, mo hùwà sí i tìfẹ́tìfẹ́, mo ṣaájò rẹ̀, mo sì gba tirẹ̀ rò.” O káre láé! Àmọ́, kì í ṣe ká kàn sọ ọ́ lọ́rọ̀ ẹnu, bí kò ṣe ṣíṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ ní àfarawé Jésù.

      21. Kí ni Jésù fi kọ́ni nípa Òfin?

      21 Ara sábà máa ń tu àwọn èèyàn ní sàkáání Jésù. Wọ́n máa ń túra ká, wọ́n máa ń rí ìṣírí gbà. Níbi tí Òfin Ọlọ́run bá ti sojú abẹ níkòó, kò sí ọ̀rọ̀ pé a tún ń yí i síbòmíràn. Níbi tí Òfin kò bá ti sojú abẹ níkòó, àwọn èèyàn lè gbé ìpinnu wọn ka ohun tí ẹ̀rí ọkàn wọn bá wí. Ìpinnu wọ́n á sì fi hàn pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run. Òfin náà jẹ́ kí wọ́n rímú mí, kì í ṣe òfin má-ṣu-má-tọ̀. (Máàkù 2:27, 28) Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn rẹ̀. Ó ń fẹ́ kó dáa fún wọn. Ó sì ṣe tán láti fojú àánú hàn sí wọn nígbà tí wọ́n bá ṣi ẹsẹ̀ gbé. Bí Jésù ṣe rí gẹ́lẹ́ nìyẹn.—Jòhánù 14:9.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́